Saturday, 2 June 2018

AGBÀLỌ́WỌ́ỌMÉRI BAÁLẸ̀ JÒNTOLO


Nínú ìwé yìí a rí Baálẹ̀ tí àwọn ará ìlú máa ń pè ní Agbàlọ́wọ́ọméri; nítorí ìwà ọ̀kánjúwà tí ó maa n wù ni wọ́n se n pe bẹ́ẹ̀, orúkọ rẹ̀ gan-an ni Àgbákànmí ṣùgbọ́n kò wu ìwà àgbà rárá[1]. Agbàlọ́wóoméri ní òré tí ó ń jé Moríyiná, ó jẹ́ asíndẹ ní ìlú Jòntolo, ó sì maa n se amín ohunkóhun tí ó bá ń lọ ní ìlú fún Baálẹ̀ Agbàlọ́wọ́ọméri. Ní ojọ́ kan tí Moríyiná lọ ta fìlà idẹ kan fún Baálẹ̀ ni ó ṣè ṣe òfófó fún Baálẹ̀ pé òun rí Aseeremasika tí ó gbé òkú oníbàárà lo sin sínú igbó ní òru mọ̣́jú. Baálẹ̀ bèèrè pé ṣé ó dá Moríyiná lójú nǹkan tí ó sọ fún òun, Moríyiná ní ìyàwó òun ni ẹlẹ́rìí. Baálẹ̀ ránṣẹ́ pe Aseeremasika àti ìyàwó rẹ̀ Olásùmíbò láti gbó tenu won. Kí Aseere àti ìyàwó rẹ̀ tó dé ilé Agbàlọ́wọ́oméri, òyì ojú ti ko Agbàlọ́wọ́ọméri, tí wọ́n da omi lé e lórí kí ó tó jí, ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n ti Aseere àti ìyàwó rẹ̀ mo ẹ̀wọ̀n di ìgbà tí ara òun yóò fi yá.

        Ọjọ́ ìdájọ́ pé, Aseere àti ìyàwó dúró ní wájú Baálẹ̀ láti sọ tẹnu wọ́n nípa ẹ̀ṣùn tí wọ́n fi kan an. Aṣeere jẹ́ ẹni rere ní ìlú Jòntolo nípa ìwà ọmọlúabi tí ó ní sí àwọn ará ìlú. Aseere  jẹ́wọ́ pé lóòótọ́ ni òun gbé òku oníbàárà lọ sin sínú igbó ṣùgbọ́n oun kọ́ ni ó pa á, pé oore ni òun ṣe nígbà tí òun rí i ní ẹ̀gbẹ́ igbó tí òtútú mú un ni òun ràn án lọ́wọ́, ṣùgbọ́n lẹ́yìn gbogbo aájò òun, ó pàpà kú. Moríyiná àti Kìmí Àdúgbò tí ó jẹ́ olóyè pàtàkì kan ní ìlú Jòntolo ti ọ̀rọ̀ sẹ́nu Aṣeere pé se ni ó pa oníbàárà nítorí owó, Aseere jẹ́wọ́ pé àpótí ni oníbàárà òun gbé fún òun. Baálẹ̀ ní kí wọ́n lo gbé àpótí náà ní ilé Aseere; nígbà tí wọ́n máa ṣí àpótí náà, wọ́n bá àjágbó ẹní àti àkíláya àtùpà elépo nínú rẹ̀. Nítorí pé Agbàlọ́wọ́ọméri àti àwọn ìjòyè rẹ̀ kó rí nǹkan gbà lọ́wó Aseere, ó pàṣẹ pé kí wọ́n gbé ọmọlanke Aṣeere tí ó fi n gbàárù sí àgbàlá òun Baálẹ̀. Aṣeere n be gbogbo wọ́n ṣùgbọ́n wọ́n kò dá a lóhùn.
          Léyin oṣù kan, ní ilé Baálẹ̀, a ri tí wọ́n de apá Aseere sẹ́yìn àti ìyàwó ní ẹ̀gbẹ́ kan tí Baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ n ṣòrò nípa ohun tí wọ́n sọ pé Aṣeere ṣe nípa ọ̀rọ̀ góòlù. Baálẹ̀ fi èsùn olè kan Aseere pé ibo ni ó ti rí góòlù àti aṣọ tí ìyàwó rẹ̀ Olásùmíbò n wò àti pé ibo ni ó ti rí góòlù tí ó fún àwọn oníbàárà. Aseeremasika tọrọ àyè pé kí àwọn obìnrin tí ó wà níbè jade kí òun lé ṣọ ibi tí ó ti rí góòlù, wọ́n jade, ó ku àwọn ọkunrin níkan síbẹ̀. Aṣeere ní òun gbọ́ tí àwọn kan sọ̀rọ̀ nípa àjágbó ẹní àti àkíláya àtùpà kan pé ẹni tí ó bá rí i gbé pé ẹni náà ti di olówó, pé ìdí ìrókò kan nínú igbó ni ẹni náà yóò ti lo àwọ́n nǹkan méjeèjì yii. Aseere ní òun pe òré òun, Àdìgún, làti fi tó o létí nǹkan tí òun gbó nítorí pé ọdẹ ni Àdìgún; àwọn méjeèjì sí gba inú igbó lọ, nígba tí wọ́n dé ìdí igi, wọ́n tan àtùpà yii, ilẹ̀kùn kan sí lára igi náà, wọ́n wọnú rẹ̀, wọ́n bá oríṣirísi ohun mèremère bíi góòlù nínú igi náà. Baálẹ̀ ní kí Aṣeere àti Àdìgún mú òun dé ìdí igi ìrókò yìí láti rí i pé òtítọ́ ni wọ́n ṣọ fún òun.
            Ní ojọ́ kejì, Agbàlọ́wọ́ọméri ránṣẹ́ pe ọmọ rẹ̀ Àkéjú láti sọ nípa ọ̀rọ̀ góòlù fún ọmọ rẹ̀ pé tí owó wọ́n bá lè te àsírí náà pé ìrandíran wọ́n kò tòsì mó laélaé. Baálẹ̀ ní ònà láti pa Aseere, Àdìgún àti Moríyiná ni òun pè e fún kí gbogbo ìsúra náà jé ti òun àti ìdílé òun. Àkéjù ní òun yóò rán àwọn kan láti pa wọ́n nígbà tí wọ́n bá n ti igbó bò ní alé, ṣùgbọ́n kí Baálẹ̀ àti Kìmí so màrìwò mó orí fún àmì ìdánimọ̀ sí àwọn ìyókù nígbà tí wọ́n bá ń ti inú igbó bò. Nígbà tí wọ́n dé inú igbó, wọ́n tan iná sí àtùpà, ilèkùn igi náà sí. Moríyiná àti Kìmí wo inú rẹ̀ láti kó góòlù, àpò mewa ni Baálẹ̀ mú dání láti kó góòlù. Aseere àti Àdìgún ti kó ìwònba ti won, ṣùgbọ́n Baálẹ̀ ní ìgbàtí àpò mewa tí òun kó wá bá tó kún ni àwọn tó máa lọ, béè iná àtùpà kò jó daadaa mó. Àdìgún so fun Baálẹ̀ pé iná kò jó daadaa mó. Baálẹ̀ bínú sọ̀rọ̀ sí Àdìgún pèlú ìbínú ó sì tèlé  Kìmí àti Moríyiná bí ó ti n kojá, ó fi ojú burúkú wo Aseere, ó sì ta Àdìgún nipa kúrò lọ́nà, Àdìgún pògìrá subú lu àtùpà, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì wo inú ihò lo léyìn igi ìrókò. Nǹkan kan dún gbàù lésè kan náà, ilèkùn ihò náà ti tì, àtùpà sì ti fó. Baálẹ̀ àti àwọn yooku rẹ̀ kò lè jade mó. Ara ta Aseere ṣùgbọ́n kò sí nǹkan tí òun tàbí Àdìgùn lè ṣe sí i, Baálẹ̀ ni ó fi ọwọ́ ara rẹ̀ ṣe ara rè. Ìwà ojú kòkòrò àti ìmọ-ti-ara-ẹni ni ó pa Baálẹ̀, Kìmí àti Moríyiná. Aseere àti Àdìgùn múra láti máa lọ ilé ṣùgbọ́n Àdìgún ní ara fun òun nípa màrìwò tí Baálẹ̀ àti Kìmí fi sí orí pé kí àwọn náà fi màrìwò sí orí pé bí ó bá jé àmì oyè ni nítòótọ̣́, àwọn náà kò ní ẹ̀ẹ̀wọ̀ oyè. Nígbà tí wọ́n dé ònà wọ́n pàdé ode meji, wọ́n ṣe bí ẹni fé ta ofà owó wọn ṣùgbọ́n wọ́n n wo màrìwò orí wọn. Àwọn ode meji yìí béèrè àwọn yooku wọn, Aseere àti Àdìgún ní àwọn kò rí àwọn tó kù, Àdìgún bèrè lówó ode keji nǹkan tí wọ́n n wá kiri nínú igbó, kàkà kí ode náà dáhùn, ohùn arò ọdẹ ni ó bẹ̀rẹ̀ sí í kọ, Àdìgún náà fi ohùn arò ode dáhùn padà, ọdẹ keji so ohun tí ó gbé wọ́n wá sí inu igbó pé ọmọ Baálẹ̀ Àkéjù ni ó rán wọ́n láti pa àwọn kan pé baba òun yóò wà níbè ṣùgbọ́n yóò so màrìwò mó orí, ṣùgbọ́n àwọn tí kò bá so màrìwò mó orí ni kí wọ́n ta lọ́fà. Àsírí Baálẹ̀ tún sí Aseere àti Àdìgún lọ́wọ́, wọ́n sì sọ fún àwọn ọdẹ pé àwọn náà ni wọ́n n dúró dè.
            Aseere àti Àdìgún padà dé ìlú, ìròyìn ti tàn lọ pé Baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ kan ti kú pé Aseeremasika ni wọ́n tèlé lo sí inú igbó kan lóru tí àwọn ọdẹ kan sì ta Baálẹ̀, Kìmí àti Moríyiná lófà, wọ́n sí kú. Aseere àti òré rẹ̀ nìkan ni ó yè. Gbogbo ara ìlú fi ìbínú wọ́n hàn pé wọ́n fé rí Àrẹ̀mọ Baálẹ̀, kí wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu Aseeremasika. Nígbà tí Àrèmọ máa sọ̀rọ̀ ó ní Aseere pa ènìyàn kan ni baba òun ní kí ó mú òun dé ibi tí ó sín ẹni náà sí. Ìyàlẹ́nu ni ó jẹ́ fún Aseere irú irọ́ tí Àrèmọ pa moó ọn. Aseere sì sọ̀rọ̀ pé ọ̀rọ̀ kò rí bí Àrẹ̀mọ ṣe só, pé Àrẹ̀mọ mó nípa ìrìnàjò lọ sí inú igbó, pé gbogbo aṣọ, owó àti góòlù tí òun rí kó nínú igbó ni Àrẹ̀mọ ti wá kó nílé òun mójú. Àwọn ara ìlú bèèrè lówó Àrẹ̀mọ ṣùgbọ́n kò rí nǹkan sọ, gbogbo ẹrù yi ni wọ́n bá nílé Àrẹ̀mọ. Àwọn ara ìlú pinu pé àwọn kò lè fi Àrẹ̀mọ Àkéjù ṣe Baálẹ̀ ìlú, pé Aseeremasika ni àwọn fé kí ó je Baálẹ̀ ìlú wọ́n nítorí oníwà rere ni Aseere jẹ́ láàrín ìlú.

 ÀWỌN ÌLÒ ÈDÈ TÍ ONKỌ̀WÉ LÒ NÍNÚ ÌWÉ ERÉ ONÍṢE AGBÀLỌ́WỌ́ỌMÉRI BAÁLẸ̀ JÒNTOLO.
ÌREMỌDẸ
Èyí wáyé laarin Àdìgún àti àwọn ọkùnrin ọdẹ méjèèjì tí wọ́n n fi ohùn arò ode bára wọ́n sọ̀rọ̀.
                                   Ọdẹ kì í kako, ọdẹ kì í ka kàkò
                                   Ọdẹ kì í se ẹnu fóró fóró fóró
Sọ ohun ikùn sílè bi òdìdè nínú oko

                                    Mo ti perin nínú igbó o
                                    Mo ti pẹfọ̀n  ní àbàtà
                                    Mo ti pa túrùkú ẹlẹ́dẹ̀ ẹgàn
                                    Ẹranko tó tó ẹranko
                                    Emi kò wá mọ kálé sòsòrò sí igbó
                                    De ọmọ elọ̀míràn bí ẹranko nínú ugbó.
                                    Bí ewúrẹ́ bá rí olóore a sáré wá o
                                    Bí ajá gòlòtò rí ẹni n bá je kí á yio ju ìrù
                                     Bí àgùtàn pòpó rí ẹlẹ́ẹ̀rí yio rìn mó ọ
                                     Àjobó òròkí olóúnjẹ kò yá á lù pa
Ẹ seun, a fé máa lo.
                                     ẹni se rere kó máa sé lọ
                                     ẹni se ìkà kó má fi sílẹ̀
                                     Oore ló pé, ìkà kò pé e jòwó jàre ẹlẹ́gbẹ́ wa.


ORIN
 Èyí wáyé nígbà tí àwọn ará ìlú Jòntolo fi Aseere jẹ ọba.
                                   Se rere o, se rere ! oore ló pé ìkà kò pé, se rere, se rere,
                                   Ìkà yio pa oníkà o, ire á bi ẹni rere,
                                   Ohun tí a bá gbìn nínú ayé o,
Yio so, yio so, ọmọ yin yio je níbẹ̀.
ÒWE
A ri àwọn òwe ti òǹkọ̀wé lò nínú ìwé Agbàlọ́wọ́méri Baálẹ̀ Jòntolo
                Ìran Kinní
                                      Ewú logbó, ìrùgbọ̀n làgbà, mamu ni ti àfojúdi
                                       Bí a bá n pa èèpo osè ara ní í fi í san
                                       Etí ọba nílé, etí ọba lóko
                 Ìran Kejì
                                       Ìtélèdí ẹni kì í rí ni tì
                                      Ọ̀rọ̀ kì í pò kí á fi ọ̀be bù ú
               Ìran Kẹrin
                                        A kì í kó imí tán ki ìkan tun máa rùn nílè
                                      Lé akátá jìnnà kí á tó ó padà bá adìe
                                      Bí iná kò bá tàn láṣọ ẹ̀jẹ̀ kì í tán ní èékán
Ìran Kẹfa
                                   Ibi ènì ni a máa pa ìyá alákàrà sí
                                   A fi oró ya oró kì í jé kí oró tán
  A kì í gbé àwòrán gàgà kí a má fi owó rẹ̀ te nǹkan

ÌWÉ ÌTÓKASÍ
Odunjo J.F (1958), Agbàlọ́wọ́ọméri Baálẹ̀ Jòntolo. Longman Nigeria Limited.


[1] Ogunruku Gbemisola Titilope ni ó kọ bébà yìí.

No comments:

Post a Comment