Ohun tí
ó kọ́kọ́ máa ń jẹ́
kàyéfi fún ẹni tí ó bá fẹ́ yẹ ipò Ọ̀mọ̀wé wò nínú àwọn ìwé ìtàn àròsọ
Yorùbá ni àwọn gan-an tí a
lè pè ní Ọmọ̀wé. ìyẹn ni pé ìbéèrè tí ó máa ń kọ́kọ́ wá sí ènìyàn lọ́kàn ni pé àwọn
wo ni Ọ̀mọ̀wé? Ìbéèrè yìí ṣòròo dáhùn ṣùgbọ́n ohun tí a ó ṣe ni pé kí á yẹ oríkì
tí ẹnì kan fún Ọ̀mọ̀wé wò. Ẹni náà ni Gutkind (1975: 22)13, ó ní:
the Ọmọwe (the educated and
wise)... are treated as honourable and fair people whether they are
poor or not. The Ọmọwe may be part of the mẹkunnu but in almost every
respect are ‘above’ the ordinary people. Many of the latter treat the Ọmọwe
as keepers of the human consicience, of what is good and eternally valuable. To
be an Ọmọwe one must not necessarily have received a higher education. There
are illiterate been honourable, who help others, who give carefully reasoned
and helpful advice. Ọmọwe do not oppress or exploit others, they want all
people to succeed. The socials status of the Ọmọwe is
not associated with cars, large houses, big parties, or well dressed women and
children – a set of features associated with the Olówo.
Lóòótọ́, kì í
ṣe gbogbo oríkì tí Gutkind (1975) fún Ọ̀mọ̀wé yìí ni àwa fi ara mọ́, síbẹ̀, a lè sọ pé ó
gbìyànjú. Fún àpẹẹrẹ àwa ò fi ara mọ́ ibi tí ó ti sọ pé Ọ̀mọ̀wé máa ń fẹ́ kí gbogbo
ènìyàn ṣe àṣeyọrí nínú gbogbo ohun tí wọ́n bá ń ṣe.
A sọ
èyí nítorí òwe Yorùbá tí ó sọ pé kò sí ẹni tí ó fẹ́ kí á dà bí òun, àfi adẹ́tẹ̀.
Èyí tí àwa kò tún
fi ara mọ́
ni ibi tí ó tún ti mẹ́nu ba pé a kì í fi ojú òǹle mọ́tò wo Ọ̀mọ̀wé. Lóòótọ́, a gbà pé
kì í ṣe gbogbo Ọ̀mọ̀wé ni ó ń lo mọ́tò ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni ó ń lo mọ́tò ní ayé
òde òní. Yàtọ̀ sí àkíyèsí méjì tí a tọ́ka sí ní òkè yìí, ó fẹ́rẹ̀ dà bí ìgbà pé
gbogbo oríkì yòókù tí Gutkind (1975) fún Ọ̀mọ̀wé ni a fi ara mọ́ nítorí pé ó da bí ìgbà pé ó
ṣe àkíyèsí àwọn Ọ̀mọ̀wé ayé àtijọ́ àti ti òde òní nígbà tí ó ń ṣe oríkì yìí. Ohun tí a
ń sọ ni
pé a lè fi oríkì tí Gutkind (1975) fún Ọ̀mọ̀wé yìí ṣe ọ̀pá ìdiwọ̀n ohun tí Ọ̀mọ̀wé jẹ́ nínú
àwọn ìwé ìtàn àròsọ wa.
Tí a bá
wá gba oríkì tí Gutkind (1975)
fún Ọ̀mọ̀wé yìí wọlé, a jẹ́ pé yóò nira fún wa láti gba pẹ̀lú àwọn
lámèyítọ́ ìtàn àròsọ Yorùbá kan tí wọn pe àwọn olú-ẹ̀dá-ìtàn kan ní
‘ordinary people’. Àwọn lámèyítọ́ yìí ni Ìṣọ̀lá (1976: 495)14 àti Barber
(1973: 37)15. Nígbà tí Ìṣọ̀lá (1976) ń fi ìdí ọ̀rọ̀ rẹ̀ múlẹ̀ nípa pé àwọn tí ó pè ní
‘ordinary people’ ni Òkédìjí kọ ìwé rẹ̀ fún, ó ní:
Okediji’s criminals are ordinary
people... the hero, Lapade, is part of the ordianry people. He lives among
them, operates among them... His tastes in food are simple and his clothes
ordinary.
Barber (1973) náà tún kín in
lẹ́yìn nípa sísọ pé:
(Lapade) has no
pretensions to the life of an alákọ̀wé
Lóòótọ́, a gbà
pé àwọn tí a lè pè ní ‘ordinary people’ ni àwọn ọ̀daràn àti àwọn tí Lápàdé ń ràn lọ́wọ́
ṣùgbọ́n ojú yòówù tí a lè fi wò ó, a ò lè ka Lápàdé kun àwọn tí a lè pè ní
‘ordinary people’. A ó ṣe àkíyèsí pé tí a bá ní kí á fi ojú oríkì
Guitkind (1975) fún
Ọ̀mọ̀wé wo Lápàdé, a ó rí i pé ara àwọn Ọ̀mọ̀wé ni a ó kà á mọ́. Gẹ́gẹ́ bí
oríkì tí Gutkind (1975) fún
Ọ̀mọ̀wé yìí, Lápàdé fẹ́ràn ọmọnìkejì, kò yan ẹnì kankan jẹ, tẹrútọmọ ló
fẹ́ràn rẹ̀, ìdí kí ó lè dára ló wà, ó sì mọ ìwé dé àyè kan nítorí wọ́n fi yé
wa pé ó ń ka ìwé
ìròyìn. Pẹ̀lú
èyí, a lè ka Lápàdé kún àwọn tí Gutkind (1975) sọ nípa wọn pé:
In almost all respect, they are ‘above’ the ordinary
people.
Ọ̀rọ̀ ẹni ti
Òkédìjí kọ ìwé rẹ̀ fún kọ́ ni ó jẹ wá lógún níyìín. Ohun tí ó fa atótónu tí a
ti ń ṣe
láti òní ni láti fi oríkì tí a lè fún Ọ̀mọ̀wé lélẹ̀. Lójú ti wa, àwọn tí a lè
pè ní ‘ordianry people’ ni àwọn tálákà tí Gutkind (1975: 12) tún sọ nípa wọn
pé:
the talaka... are ...
characterized ... as those who push carts and “carry loads on their heads” ...
The talaka come closest to what can be called the dispossessed.
Tí a bá gba
oríkì yìí, a jẹ́ pé irú àwọn Salami Kemberu ni a lè gbà gẹ́gẹ́ bí ẹni tí
àwọn lameyitọ tí a mẹ́nu bà lókè yìí ń pè ní ordinary people’ tí àwa túmọ̀ sí tálákà.
Nígbà tí ọwọ́ Lápàdé ba Sàlámì yìí tí ó sì sọ ìdí tí ó fi ń jalè, ó sọ pé:
Mo rìn
rìn rìn, mo pààrà pààrà, mo rin gbogbo ilẹ̀ yí, ng ko ri ẹni gba mi ṣíṣẹ́
kankan. Ẹ beere lọ́wọ́ àwọn kọ̀ráà ní Gbági. Ẹ lọ bèèrè ní Sekiteria
lórítamẹ́fà. (Àjà Ló
Lẹrù Pg. 51)
Irú àwọn
ẹ̀dá-ìtàn tí ó wáṣẹ́ tí kò rí iṣẹ́ yìí ni àwa lè ka kún ‘ordinary people’ tí
àwa túmọ̀ sí tálákà. Ó kéré
tán, a ó ka irú Lápàdé yẹn kún ara àwọn kòlà-kòṣagbe. Tí ìwé Òkédìjí bá fẹ́
tẹ̀lẹ́ ohun tí Barber (1979: 37)16 sọ wí pé:
His two novels show a profound
sympathy with the ordinary people who hae not made it into the elite.
ń ṣe ni ó yẹ kí
ó wá ọ̀nà tí irú àwọn Sàlámì yìí yóò fi rí iṣẹ́ ṣe tí ọ̀rọ̀ à-ń-ja-olè kò fi ní
í jẹ wọ́n lógún. A sì ti rí àpẹẹrẹ irú ẹni tí ó kọ irú ìwé báyìí.
Àpẹẹrẹ irú ìwé báyìí ni ti Treassel (1965)17 tí Nazareth (1967:
35)18 sọ nípa rẹ̀ pé:
(He) designed to show the
conditions resulting from poverty and unemployment to expose the futility of
the measures taken to deal with them and to indicate what (He) beleives to be
the only real remedy, namely socialism ... he presents ... a faithful picture
of working class life... more especially of
those engaged in the Building trades... we see and feel for ourselves the
injustice, oppression, inhumanity, brutality and degradation suffered by those
people.... Tressell is angry – he is angry ... with the employers .... who
inflicts injustice on their workers out of self interest ... people always take
great care of their horses. If they were to work their horses to death, they
would have to buy another, if they work a man to death, they can get another
for nothing at the corner.
Ohun tí a kàn ń fi gbogbo ohun
tí a ń sọ
láti òní ṣe àlàyé ni pé ògo àwọn Ọ̀mọ̀wé ni Òkédìjí ń fi Lápàdé gbé ga
nínú àwọn ìwé rẹ̀ méjèèjì. Báyìí náà ni Akínlàdé ṣe lo Akin Olúṣínà náà nínú
àwọn ìwé ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ tirẹ̀. Lóòótọ́, àwọn ènìyàn máa ń ṣe àpèjúwe
Olúṣínà gẹ́gẹ́ bí:
ọkùnrin onitubomu to (máa ń) di tayi mọrun
pọn-pọn-pọn
síbẹ̀, lójú ti wa, kò
sí ìyàtọ̀ kan dan-in dan-in láàrin òun àti Lápàdé. Ipò Ọ̀mọ̀wé kan náà ni a lè
kà wọ́n sí. Ohun tí ó kàn ń ṣẹlẹ̀ kò ju ohun tí Mercier (1966: 379)19
ṣe àkíyèsí wí pé:
... between the elites themselves the relationship
fluctuates
ìyẹn ni pé ẹni
tí ó bá ka Lápàdé àti Olúṣínà sí ẹgbẹ́ àti ọ̀gba kò jayò pa.
Gẹ́gẹ́
bí a ṣe sọ tẹ́lẹ̀, ohun tí a kàn ti ń gbìyànjú láti ṣe ni láti fi ìdí àwọn tí a lè pè
ní Ọ̀mọ̀wé lélẹ̀ kí á sì sọ ìyàtọ̀ tí ó wà láàrin wọn àti ohun tí àwọn kan
pè ní “ordinary people” tí àwa túmọ̀ sí tálákà èyí tí a kò ka àwọn Ọ̀mọ̀wé mọ́
ní ti wa.
Lẹ́yìn
ìgbà tí a ti mọ àwọn tí a lè pè ní Ọ̀mọ̀wé yìí, a lè wá bèèrè pé irú ìhà wo
ni àwọn òǹkọ̀wé wa
kọ sí àwọn Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́ wọn? Ṣé tí a bá wo àwọn tí ó ń kọ ìtàn àròsọ
ní èdè míiràn, ohun tí a ó ṣe àkíyèsí ni pé bákan méjì ní èrò wọn nípa
Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́ wọn. Wọ́n lè jẹ́ kí ọ̀rọ̀ Ọ̀mọ̀wé jẹ wọ́n lógún. Bó wù wọ́n, wọ́n
lè gbé ọ̀rọ̀ kalẹ̀ bí àwọn Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́ wọn yóò ṣe gbé e kalẹ̀, bó sì wù
wọ́n, wọ́n lè máà ṣe bẹ́ẹ̀. Fún àpẹẹrẹ, tí a bá wo The Interpreter, ìwé tí
Ṣóyínká kọ lórí àwọn Ọ̀mọ̀wé gan-an, ibi tí ó ti sọ̀rọ̀ lórí ohun tí ó ń lọ gẹ́gẹ́ bí
àwọn Ọ̀mọ̀wé yóò ṣe sọ ọ́ kò pọ̀ rárá. Àkíyèsí èyí ni Ogundipẹ-Lesilie
(1981: 3)20 ṣe lẹ́yìn ìgbà tí ó ti yẹ ìwé náà wò tí ó fi sọ pé
…hold an intellectual discussion of important issues and
this they do in a rather disjointed and distracted manner... It may be argued
that four times is not inconsiderable in a novel whose time-span is so brief
but this is a novel about intellectuals.
Ọ̀rọ̀ àwọn tí ó
ń kọ ìtàn àròsọ
Yorùbá kò rí báyìí. Ó dàbí ìgbà pé ìtàn àròsọ wọn tí kò dá lórí Ọ̀mọ̀wé
pàápàá, yàtọ̀ sí ti pé wọn yóò gbé ìrírí wọn hàn wá gẹ́gẹ́ bí Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́
wọn yóò ṣe gbé e hàn wá, ọ̀rọ̀ Ọ̀mọ̀wé ni ó máa ń jẹ wọ́n lógún.
Nǹkan tí èyí ń fi hàn ni pé
ìhà tí àwọn òǹkọ̀wé
ìtàn àròsọ Yorùbá kọ sí àwọn Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́ wọn yàtọ̀ sí èyí tí wọ́n kọ sí
ipò ọba. Ṣé ní ti ọba, a lè rí
àwọn òǹkọ̀wé
kan tí ó jẹ́ pé ipò tí àwọn ọba yìí wa ní ayé àtijọ́ sì ń wù wọ́n, wọ́n ń fẹ́ kí ayé padà
sí ibi àárọ̀. Àwọn míràn sì wà tí ó jẹ́ pé wọ́n ń fẹ́ kí àyípadà
dé bá àwọn ọba yìí. Lójú àwọn òǹkọ̀wé tí ó ní irú èrò yìí, bí a ṣe bí ẹrú ni a bí
ọmọ. Nípa ti ọ̀rọ̀ ipò ọba yìí kan náà, àwọn òǹkọ̀wé kan wà tí
a kò mọ ibi tí ó yẹ kí á to wọ́n sí. A sì ti sọ ohun tí a rò pé ó fà á tí
àwọn ohun tí a ṣe àkíyèsí yìí ṣe rí bẹ́ẹ̀. Ṣùgbọ́n tí a bá wo ipò Ọ̀mọ̀wé
nínú àwọn
ìtàn tí ó ń kọ
ìtàn àròsọ wa, ọ̀kan náà ni wọ́n. Ìyẹn ni pé omi ẹ̀kọ, ẹ̀kọ ni. Bóyá èyí ni
ó fà á tí
ó fi jẹ́ pé ń ṣe ni
gbogbo àwọn òǹkọ̀wé wa
sùn tí wọ́n kọ orí sí ibi kan náà nípa ọ̀rọ̀ Ọ̀mọ̀wé. Ṣé àkéké tó kégi nígbó ni ọ̀rọ̀ yìí,
orí ara rẹ̀ ni ó ń ké. Mo rò
pé èyí ní ó fà á tí àwọn òǹkọ̀wé wa kò fi ń fẹ́ sọ̀rọ̀ òdì púpọ̀ sí àwọn Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́ wọn.
Yàtọ̀ sí
ti pé ẹgbẹ́ àti ọ̀gbà kan náà ni òǹkọ̀wé àti Ọ̀mọ̀wé yìí jọ wà, a ó tún ṣe àkíyèsí pé
àwọn Ọ̀mọ̀wé yìí gan-an ni
àwọn òǹkọ̀wé ní
lọ́kàn nígbà ti wọ́n ń kọ ìwé
wọn. Ọ̀pọ̀ ìgbà ni ó jẹ́ pé eléyìí kì í ṣe ìfẹ́ inú wọn. Àwọn tí ó máa ń bá wọn tẹ ìwé
wọn jáde ló máa ń fà á ní
ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà. Ṣé a
mọ̀ pé nítorí kí wọn lè jèrè ni àwọn òǹtẹ̀wé ṣe ń tẹ ìwé jáde.
Ohun tí ó sì máa ń jáde ni
ẹnu àwọn òǹtẹ̀wé yìí ni pé ṣe wọn yóò ra a? Nítorí ìdí èyí,
àwọn ìwé tí Ọ̀mọ̀wé àárín wa yóò rà ni wọ́n máa ń fẹ́ tẹ̀ jáde.
Tí a bá sì fi ìwé pẹ̀gàn ènìyàn, bóyá ni yóò ṣe rà á.
Órí ìwé Fágúnwà
ni a ó ti bẹ̀rẹ̀ sí níí yẹ ohun tí àwọn òǹkọ̀wé sọ nípa àwọn Ọ̀mọ̀wé wò. Nígbà tí Fágúnwà ń kọ̀wé rẹ̀,
àwọn Ọ̀mọ̀wé ṣẹ̀ṣẹ̀ ń dìde
ni. Níwọ̀n ìgbà tí ó sì ti jẹ́ pé wọn ò pọ̀, ọwọ́ wọn ni gbogbo iṣẹ́ tí ó
wà ní ìgbà náà gẹ́gẹ́ bí olùkọ́, akọ̀wé kóòtù, lééridà àti àwọn irú iṣẹ́ báwọ̀nyí
máa ń bọ́ sí.
Irú àwọn Fágùnwà yìí ni ó fi ara wọn sí ipò agbẹnusọ fún
àwọn ènìyàn wọn. Fágúnwà ní tirẹ̀ tilẹ̀ sá sọ ọ́ di iṣẹ́ gidi gan-an ni. Tí a bá wo
àdúrà tí ó ṣe ní ìparí Ògbójú Ọdẹ Nínú Igbó Irunmalẹ̀ tí ó fi sọ pé
Orilẹ
ede yin yio tubọ ma pọ si ni ọgbọn ati ni agbara, awa enia dudu ko ni ire
ẹhin mọ lailai.
(Pg. 95).
a ó rí i pé
àdúrà yìí wá láti ẹnu ẹni tí ó gbà pé orílẹ̀ èdè yìí kò gbọ́n tẹ́lẹ̀ àti pé
ni ẹ̀yìn ni orílẹ̀ èdè yìí wa. Ohun tí ó yẹ kí á bí ara wa ni pé kí ni Fágúnwà
fi ṣe ọ̀pá ìdiwọ̀n wí pé orílẹ̀ èdè yìí kò gbọ́n àti pé ó wà ní ẹ̀yìn? Ohun tí
ó fi ṣe ọ̀pá ìdiwọ̀n kò ju àṣà àwọn ará òkè òkun lọ. Ìyẹn ni pé ni ojú
Fágúnwà, ọ̀nà kan tí orílẹ̀ èdè yìí fi lè máa ga sí i ni nípa kíka ìwé èyí tí
òùn àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀ ti ṣe. Bẹ́ẹ̀, ohun tí Yorùbá máa ń sọ ni pé ìwé
kò kan ọgbọ́n. Èyí tilẹ̀ fi hàn pé Yáì (1977: 6)21 ṣe àkíyèsí
Fágùnwà gan-an ni kí
ó tó sọ pé lóòótọ́, ìdílé mẹ̀kúnnù ni Fágúnwà ti wá ṣùgbọ́n ohun tí ó ń gbìyànjú láti
ṣe ni pé kí ó fi ipò yìí sílẹ̀ kí ó sì da ara pọ̀ mọ́ àwọn tí a lè pè ní
Ọ̀mọ̀wé, àwọn tí ó jẹ́ pé àwọn ni a ń fi ojú iyì àti ẹ̀yẹ wò ní ayé àtijọ́. Yáì (1977: 6) ní
his “source class” so to speak is
the Yoruba poor peasantry, his “target class” was undoubtedly the urban petty
bourgeoisie
Ọ̀nà kan tí
Fágúnwà sì fi lè ṣe èyí ni pé kí ó ka ìwé nítorí lójú tirẹ̀ bí wọn kò bá ní ọlá ní
òní,
Oni, nwọn mbọ wa ni lọla
Abájọ tí Fágùnwà fi sọ ọ̀kan
nínú àwọn
òbí olú-ẹ̀dá-ìtàn rẹ̀ kan ní Akọ̀wédìran. Mo rò pé èyí kan náà ni Yáì (1977:
10)22 rí tí ó ṣe pé olú-ẹ̀dá-ìtàn yìí ní
... conformist, reactionary and
egoist who is completely deaf to the problem of the Nigerian masses
Tí a bá
tilẹ̀ fi ojú inú wo ìwé Fágúnwà, a ó rí i pé bí ẹni ń ṣe iṣẹ́
olùkọ́ gan-an ni ó
ka iṣẹ́ tí ó ń ṣe sí.
Ó sa gbogbo ipá rẹ̀ láti fi ẹ̀sìn àwọn ọmọ lẹ́yìn Kírísítì han àwọn tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ tí wọ́n
fẹ́ dára pọ̀ mọ́ àwọn Ọ̀mọ̀wé. Kò dà bí ìgbà pé gbogbo ohun tí ó jẹ́ ti ilẹ̀
wa jẹ ẹ́ lógún rárá. Fún àpẹẹrẹ, nínú Ògbójú Ọdẹ Nínú Igbó Irúnmalẹ̀,
nígbà tí àwọn ọdẹ ń lọ sí
Òkè Láńgbòdó tí
wọ́n kọjá Igbó Irúnmalẹ̀ tán, ohun abàmì kan ṣẹlẹ̀ sí wọn. Ṣe ni wọ́n dédé
rí i tí igbó bẹ̀rẹ̀ sí níí yí wọn po tí wọn kò sì rí ojú ọ̀nà mọ́. Wọn kò lè
yá sí ọ̀tún bẹ́ẹ̀ ni wọn kò lè yà sí òsì. Iwájú ò ṣeé lọ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yìn ò
ṣeé padà sí. Wọ́n tilẹ̀ ní igbó náà dí débi tí ó fi jẹ́ pé èkúté pàápàá kò lè
rí ibi gbà kọjá. Ó ṣe ni ẹyẹ kan sọ pé àfi tí wọ́n bá pa oùn tí wọ́n sì fi
òun rúbọ ni inú Ọlọ́run yóò fi lè dùn sí wọn. Wọ́n pa ẹyẹ yìí lóòótọ́,
wọ́n sì fi i rúbọ. Fágúnwà ní
Gẹ́gẹ́
bí àṣà ilẹ wa, a mu ẹiyẹ yi a la inu rẹ̀ a bu epo si i a si gbe e sinu
apadi kekere kan bayi a gbe e lọ si idi igi nla kan ti mbẹ lẹba ọdọ wa.
Inu Ọlọrun dun pe a ronupiwada – ki ise nitori ẹbọọ ti a ru – ṣugbọn
nitori o mọ̀ pe ibaṣepe a ni oye jubẹ lọ ni, a ba sin on ni ọna ti o dara
ju eyini lọ
A ó ṣe àkíyèsí
pé bí àwọn ènìyàn yìí ṣe sin Ọlọ́run ni ọ̀nà ìbílẹ̀ wa yìí kò tẹ́ Fágúnwà
lọ́rùn rárá. Àwọn tí ó lóye lójú tirẹ̀ ni àwọn Ọ̀mọ̀wé tí wọ́n ń sin Ọlọ́run ní ìlànà tí àwọn ọmọlẹ́yìn
Kírísítì.
Ọ̀rọ̀ ti
pé a ń gbé
ọ̀rọ̀ eẹni tí ó mọ̀wé lárugẹ yìí tilẹ̀ fẹ́rẹ̀ máà jẹ́ kí á lè gba ìtàn
Fágúnwà gbọ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà. Ní inú Igbó Olódùmarè, ohùn ẹni tí ó
ń sọ ìtàn yìí
fún wa ni a kọ́kọ́ gbọ́ tí ẹnì kan pè pé kí ó wá máa kọ ìtàn kan sílẹ̀. Ìtàn tí
wọ́n ń kọ sílẹ̀
yìí kì í ṣe ti ẹni tí ó ń sọ ọ́, ti baba rẹ̀ ni. Nígbà tí ó ṣe, kò kúkú sọ ìtàn
yìí mọ́, ń ṣe ni
ó bẹ̀rẹ̀ sí níí kà á níbi tí baba rẹ̀ kọ ọ́ sí. Èyí fi hàn pé ẹni tí ó ń sọ ìtàn yìí
mọ ìwé. Bẹ́ẹ̀ rè é, ọdẹ sì ni. Ohun tí a rí ṣe ní àlàyé ni pé ó ní láti ti
lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ kí ó tó
bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ọdẹ. Kàyééfì gbáà ni eléyìí. Tí a bá fi ojú inú wo àsìkò tí
Fágúnwà ń kọ ìwé
rẹ̀, a ó rí i pé yàtọ̀ sí ti pé ọdẹ kò lè mọ-ìwé-kọ-mọ̀-ọ́n-kà, kò ṣeé ṣe
kí baba ẹni tí ó jẹ́ ọdẹ yìí tún mọ ìwé kọ pẹ̀lú. Ṣùgbọ́n Fágúnwà kò ro
èyí jinlẹ̀ nígbà tí ó ń kọ ìwé
rẹ̀ nítorí ohun tí ó jẹ ẹ́ lógún, ìyẹn ìgbéga àwọn Ọ̀mọ̀wé. Ní òde òní pàápàá
tí àwọn Ọ̀mọ̀wé kò rí iṣẹ́ ṣe tó bẹ́ẹ̀ jù bẹ́ẹ̀ lọ mọ́ yìí, a ò tí ì rí
Ọ̀mọ̀wé tí ó finúfẹ̀dọ̀ sọ pé iṣẹ́ ọdẹ ni ó wu òun.
Tí a bá
tilẹ̀ wo ohun tí Barber (1979: 25)23 pè ní àléébù nínú ìwé Fágúnwà,
a ó rí i pé ọ̀nà àtigbé ọ̀rọ̀ Ọ̀mọ̀wé lárugẹ ni ó fa àléébù yìí. Barber (1979) ní a kì í mọ
ohùn ẹnì kan yàtọ̀ sí ti èkejì. Irú gbólóhùn kan náà ni Fágúnwà máa ń lò léra léra.
Ibáà ṣe pé ó ń wàásù
ni tàbí pé ó ń sọ
ọ̀rọ̀ ìjà. Bí àgbàlagbà ń sọ̀rọ̀,
bákan náà ni yóò rí sí ti ọmọdé. Bí ó ṣe òǹkọ̀wé pàápàá ni ó ń ṣe àyàbá tí ó
ń dá sí ohun tí
àwọn ẹ̀dá-ìtàn ń sọ, a
kì í ṣe àkìyèsí ìyàtọ̀ kankan. Ní ìparí, Barber (1979) ní ẹnikẹ́ni yòówù tí ó ń sọ̀rọ̀, ibikíbi yòówù tí
ó ti ń sọ ọ́,
bí ẹni ń gba
ohùn Fágúnwà sọ ni ó máa ń rí.
A gbà
pẹ̀lú gbogbo ohun tí Barber (1979) ṣe àlàyé yìí ṣùgbọ́n kò fi ìdí tí
Fágúnwà ṣe ṣe èyí yé wa. Ohun tí ó fà á tí Fágúnwà fi ṣe èyí ni pé ó fẹ́ kọ
ìwé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe tọ́ kí Ọ̀mọ̀wé kọ ọ́ sílẹ̀. Ó fẹ́ kọ ọ́ ni ọ̀nà tí ó tọ̀nà
fún kíkọsílẹ̀ èdè Yorùbá. Ohun tí ó fà á gan-an nì yí tí kò fi fẹ́ kí èdè tí ẹnì kan
bá sọ nínú ìwé òun yàtọ̀ í ti ẹlòmíràn. Tí ó bá ṣe èyí, lójú tirẹ̀, àgbékalẹ̀ rẹ̀ kò ní í bá
èyí tí àwọn Ọ̀mọ̀wé mu.
Tí a bá
tilẹ̀ kúrò lórí ìwé Fágúnwà tí a yẹ àwọn ìwé tí a kọ jáde láìpẹ́ wò, lékèe
wí pé Yáì (1977: 7) sọ pé
Nowadays, people attach more
importance to being an alhaji, a major,
(a businessman) than to being a professor
Ìyẹn ni pé
àwọn alhaji, àwọn ológun àti àwọn oníṣòwò ni ó gbajúmọ̀ jù ní àwùjọ wa
lónìí tí ó sì jẹ́ pé àwọn Ọ̀mọ̀wé kò rí ipò kan tí ó dára kó, síbẹ̀, ọ̀pọ̀ nínú
àwọn tí ó n kọ ìtàn àròsọ wa ló jẹ́ pé ọ̀rọ̀ nípa à ń lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ ni ó jẹ wọ́n
lógún. Kì í ṣe pé a sọ pé ohun tí wọ́n ṣe yìí kò dára, ṣùgbọ́n ohun tí a
ṣe àkíyèsí ni pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ìwé ìtàn àròsọ yìí ni ó jẹ́ pé awọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́
báyìí ni wọ́n fi bojú ohun tí wọ́n kọ sílẹ̀ tí ó jẹ́ pé ìgbésí ayé wọn gan-an ni wọ́n kọ
sí ìta fún wa kà. Tí a bá
wo Kékeré Ẹkùn àti Àyànmọ́, díẹ̀ ni gbogbo ohun tí a mẹ́nu bà
nínú ìwé méjèèjì yìí fi yàtọ̀ sí ìgbésí ayé Ọlábímtán fúnra rẹ̀. Bákan náà ni
ó ṣe jẹ́ pé ó fẹ́rẹ̀ jẹ́ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí Akínwùmí Ìṣọ̀lá ní
Yunifásítì Ìbàdàn ni ó kún inú Ó Le Kú tẹ́tẹ́.
Ní ìgbà míràn,
tí àwọn òǹkọ̀wé
yìí kò bá sọ ìtàn ìgbésí ayé wọn, wọn yóò sáà wá ọ̀nà láti fi hàn wá pé
ọ̀rọ̀ ìwé kò ṣeé mú yẹpẹrẹ. Nínú Aiyekootọ, ọ̀rọ̀ nípa bí
Ọpẹ́yẹmí ṣe lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ ni ó fẹ́rẹ̀ gba ìlàjì ìwé ọ̀hún tán. Bí àwọn onígbàgbọ́
ṣe ń kọ́
ẹ̀kọ́ àgbà àti bí ìwé kíkà ṣe gbé Déòtí gòkè àgbà ni ohun tí ó kan Ládélé
gbọ̀ngbọ̀n nínú Jẹ́ N Logba Temi. A tilẹ̀ fi dandan lé e pé ẹni tí
ó bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gba ẹ̀sìn ọmọ lẹ́yìn Kírísítì gbọ́dọ̀ kọ́ ẹ̀kọ́ àgbà bí
Bánkọ́lé ṣe ń kọ́
bi-à-ba, bí-e-bè, bí-ẹ̀bẹ
bí-ì-bi ... bí-ọ̀-bọ (Jẹ N Logba
Temi, Pg. 16).
Kí á
tilẹ̀ ní a kúrò lórí àwọn òǹkọ̀wé tí wọ́n ti sọ ìwé wọn di agbátẹrù bí a ṣe ń kọ́ ọmọ ní
ìwé, ọ̀pọ̀ nínú ìwé tí wọ́n ṣe bí ẹni pé àwọn kò polongo ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́
pàápàá, ohun tí wọn mẹ́nu bà nípa Ọ̀mọ̀wé kúrò ní díẹ̀. Ohun tí a ṣe àkíyèsí
pé ó pọ̀ jù nínú àwọn ìwé ìtàn àròsọ yìí ni pé àwọn tí ó kọ wọ́n gbà pé nǹkan Gẹ̀ẹ́sì
sunwọ̀n ju ti wa lọ. Àwọn nǹkan Gẹ̀ẹ́sì yìí ni wọ́n fi ṣe àwòrán ojú inú tí ó dúró fún
Ọ̀mọ̀wé, ìyẹn ni pé a lè pe àwọn nǹkan Gẹ̀ẹ́sì tí a mẹ́nu bà yìí ní àwọn ohun tí wọ́n
fi pàrokò fún Ọ̀mọ̀wé. Nínú ìwé Délànọ̀, àwọn onígbàgbọ́ ni ó jẹ́ kí ó dúró
fún àwọn nǹkan
Gẹ̀ẹ́sì yìí, ó ní
Gbogbo obi
igbana a ma ṣofu ọmọ pupọ nitori iwa ope àti aigbọn... Tani jẹ ko iyan
onigbagbọ kere ... eto iwosan àti ilera wa ni sakani wọn. bi wọn ti kere to
ọga ni nwọn jẹ fun awọn keferi ti nwọn jijọ nbe ladugbo (Aiye Daiye
Oyinbo, Pg. 61)
A ó ṣe àkíyèsí
nínú àyọlò òkè yìí wí pé kì í ṣe pé wọ́n ka ẹ̀sìn àjèjì yìí sí nìkan ni, wọ́n
tún fẹnu tẹ́ńbẹ́lú
èyí tí ó jẹ́ ti wa. Èyí tí Délànọ̀ ìbá fi pè é ní ẹ̀sìn ìbílẹ̀, kèfèrí ni ó pè
é. Lójú Délànọ̀, kò sí ìdí méjì tí àwọn òbí yìí fi ń ṣòfu ọmọ bí
kò ṣe ti pé wọn kò kọ́ ẹ̀kọ́ mọ̀-ọ́n-kọ mọ̀-ọ́n-kà tí àwọn ọmọ lẹ́yìn
Kírísítì yìí gbé dé lọ.
Ọ̀rọ̀
àìní ìfẹ́ ohun ìbílẹ̀ wa kan náà ni a ṣe àkíyèsí nínú Kékeré Ẹkùn.
Ọlábímtán gbìyànjú láti rí i pé àṣà Òyìnbó borí ti Yorùbá. Bí a ṣe yí Bádéjọ
padà sí ìgbàgbọ́ jẹ́ kàyééfì gbáà. Àwọn ẹgbẹ́ ọ̀jẹ̀ kò tilẹ̀ janpata. Ó tilẹ̀
ṣe wá jẹ́ pé àlùfáà gan-an ni ó
wá ṣe kòńgẹ́ igi
tí a jù lu Àlàbí? A ó tún ṣe àkíyèsí pé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí Bádéjọ náà ló
ṣẹlẹ̀ sí Bánkọ́lé nínú Jẹ́ N Logba Temi. Yàtọ̀ sí èyí, a ó tún ṣe
àkíyèsí pé ọṣẹ́ tí egbòogi ìbílẹ̀ ṣe fún ọmọ kan ló jẹ́ kí Àlàbí fẹ́ kọ́
iṣẹ́ ìṣègùn nínú Àyànmọ́ nítorí oníṣègùn òyìnbó ló gba ọmọ tí àìsàn
yìí ń ṣe là.
Ǹjẹ́ a lè wá torí
èyí gba ohun tí Lamming (1973: 61)25 sọ gbọ́ pé “the colonial
system taught us much more about the mother country than about ourselves”.
Ìyẹn ni pé ìjẹgàba lẹ́ni lórí tí àwọn Gẹ̀ẹ́sì jẹ gàba lé wa lórí, ń ṣe ni wọ́n fi
ń kọ́ wa ní ohun
tí ó jẹ mọ́ ilẹ̀ wọn tí wọ́n sì ń tẹ ti ilẹ̀ wa rì. Lójú ti wa, a rò pé a lè gbà
pẹ̀lú rẹ̀ mọ̀nà. A sáà rí i tí àìmọ̀wé Ọláńrewájú ń dún ìyá rẹ̀ sùn-ùn-ùn nínú Aiye Dáiye Oyinbo. Bẹ́ẹ̀ a sì mọ̀ pé ọ̀kan
nínú àwọn ohun tí àwọn Gẹ̀ẹ́sì yìí fi sílẹ̀ fún wa ni ẹ̀kọ́ mọ̀-ọ́n-kọ
mọ̀-ọ́n-kà. Ọ̀rọ̀ tí pé ọmọ mọ̀-ọ́n-kọ mọ̀-ọ́n-kà yìí tilẹ̀ ká ìyá Ọláńrewájú tí a ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí lára débi tí
ó fi sọ pé ìyá jẹ òun. Ó ní ọmọ òun ìbá mọ̀wé ìbá di ènìyàn ńlá lójijì. Ìyẹn
ni pé ìwé mímọ̀ nìkan ni ó ń sọ ni di ènìyàn ńlá. Bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lójú àwọn òǹkọ̀wé wa nì yí.
Àìmọ ìwé wá di ohun àbùkù bẹ́ẹ̀ rè é nǹkan kan ni adìyẹ ń jẹ kí àgbàdo tó dé ilé ayé. Àṣà
Òyìnbó wọ Bámidélé lẹ́wù tán nínú Gbọ́baníyì débi pé bí ó bá ń jẹun lọ́wọ́ tí
àlejò bá dé, kì í pè
é wá jẹun, kò tilẹ̀ ní í jẹ́ kí irú ẹni bẹ́ yẹn mọ̀ pé ń ṣe ni òun ń jẹun lọ́wọ́.
Lójú Yemitan, àṣà tó dára ni, “ajẹ̀rù ni” irú ẹni tí ó bá bá ni ní orí oúnjẹ
tí ó ti ọwọ́ bọ̀ ọ́. Irú ohun tí kì í ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ wa tẹ́lẹ̀ nì yí tí ó jẹ́
pé ṣe la máa ń ro
àlejò mọ́ oúnjẹ wa. Jọkẹ́ tilẹ̀ bínú pé àbúrò Àlàbí tí ó wá kí òun kò kọ́ kọ
ìwé ṣáájú nínú Àyànmọ́. Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí, àwọn òǹkọ̀wé wa kò kọ
wọ́n ní ìtẹ́ńbẹ́lu
tàbí ní ìbu ẹnu àtẹ́ lù, ń ṣe ni wọ́n ń kọ wọ́n ní ọ̀nà tí yóò fi gbe ògo àwọn Ọ̀mọ̀wé
ga.
Ní ayé
àtijọ́, nígbà tí àwọn Gẹ̀ẹ́sì ṣẹ̀ṣẹ̀ gòkè ni Awóníyì tún gbé wa lọ nínú ìwé
rẹ̀ Aiyekootọ. Ní ìgbà yẹn, gbogbo iṣẹ́ tí ó bá ti gbajúmọ̀ ni ó máa
ń jẹ́ ti àwọn
Ọ̀mọ̀wé. Àwọn ni kò-sí-ní-àjọ-àjọ-ò-kún. “Hẹẹ́dì” tí Awóníyì lò bí aṣojú
àwọn Ọ̀mọ̀wé níyìín ni
Oníwàásù
ijọ, òun kan náà ni atẹduuru... ọga àwọn akọrin... ogbifọ... Bí ọ̀rọ̀ kan
ṣe pàtàkì ni abule, lẹhin Baalẹ oun naa ni o kan... omiran tilẹ ro pe
Dokita ni gbogbo ẹni tí o bá ti mọ iwe, nitorina bi ọ̀rọ̀ kan ba ti de nipa
aisan, o di ọdọ Hẹẹdi (Aiyekootọ, Pg. 28).
Àwọn nìkan ni ó
mọ ohun tí ó tọ́ tí ó mọ ohun tí ó yẹ gẹ́gẹ́ bí Fílíbì ṣe fi ọgbọ́n sọ̀rọ̀
sí Baba Bámidélé nínú Gbọ́baníyì nítorí tí ó tutọ́ sí ilẹ̀ ilé lásan. Ó
ní
Bí
Fílíbì ti jokòó tan, baba Bamidele sana si ikoko, ... o tutọ silẹ... Ara
Filibi ṣọgbọn kọ ọ, ó sì rọra ki ọgbọn alakọwe bọ ọ. Baba ẹ jẹ ka
bọ si ẹgbẹ ita
jokòó ki ẹ le raye maa tutọ. Awọn ọga wa nile-iwe lo maa nsọ fun wa pe
ka maa tutọ sinu ile (Gbọ́baníyì, Pg. 20).
Bẹ́ẹ̀ sì rè é,
Fílíbì tí ó ń pẹ̀gàn
ẹni tí ó ń mu ìkòkò tí ó ń tutọ́ sílẹ̀ yìí
ni a fi yé ni pé sìgá mímú ti di bárakú fún ṣùgbọ́n nítorí pé Fílíbì jẹ́
ọ̀mọ̀wé tí òǹkọ̀wé
fẹ́ gbé ní arugẹ, kò bu ẹnu àtẹ́ lu sìgá mímu Fílíbì yìí dàbí alára.
A ó ṣe
àkíyèsí wí pé tí a bá rí Ọ̀mọ̀wé kan tí ó ń ṣi ìwà hù, àwọn òǹkọ̀wé wa kò ní í fẹ́ kí á fi ojú Ọ̀mọ̀wé
lásán wò wọ́n. Wọn yóò ti ọ̀rọ̀ wọn mọ́ nǹkan míràn lọ́rùn. Wọ́n lè sọ wọ́n di olóṣèlú tàbí
oníṣòwò pàtàkì. Tí wọ́n bá ti lè sọ wọ́n di irú nǹkan wọ̀nyí, wọ́n
lè wá sọ ohun tí ó bá wù wọ́n nípa wọn. Irú àwọn ẹni tí àwọn òǹkọ̀wé wa ṣe
báyìí ṣe ni Délé nínú Gbọ́baníyì àti Dúró nínú Baba Rere. Délé
tí kò kọ ibi ara sí ọ̀rọ̀ ìwé ní ìlú òkèèrè dé wá ń du ipò ìlú
ṣíṣe. Àìtó owó tí ìbá rí ná láti fi gba iyì gba ẹ̀yẹ ni ó mú Délé gba rìbá.
Bákan náà ni Dúró tí a gbé hàn wá gẹ́gẹ́ bí oníṣòwò bẹ̀rẹ̀ sí máa ṣe
ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìbàjẹ́ láti fi lè ní owó lọ́wọ́. Ó n gé ẹfun mọ́ òògùn. Ó ń kó ẹrù
fàyàwọ́. Ó tilẹ̀ pa ènìyàn nítorí owó. Àìfi wọ́n sí ipò Ọ̀mọ̀wé ni ó jẹ́ kí
àwọn òǹkọ̀wé wa
ṣe báyìí gbé wọn hàn wá.
Ni ti
wa, a rò pé àwọn òǹkọ̀wé wa
kò fi ayé Ọ̀mọ̀wé wa hàn wá tó bí ó ṣe tọ́ àti bí ó ṣe yẹ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe
ṣe fún àwọn ọba. Tí a bá wo àwùjọ wa, gẹ́gẹ́ bí a ṣe sọ ṣáájú, a ó ṣe
àkíyèsí pé àwọn oníṣòwò àti àwọn olóṣèlú ni ayé tún wà ní ọwọ́ wọn báyìí.
Ó dàbí ìgbà pé àwọn òǹkọ̀wé wa
ti tẹnpẹlẹ mọ́ ipa ti Ọ̀mọ̀wé jù. Bẹ́ẹ̀ rè é, Ògungbẹ̀san (1971: 61)26
ti sọ̀rọ̀ tán, ó ní
If literature is relevant at all it is because we obtain some pciture of
society and of life from it
Ìyẹn ni pé tí
lítíréṣọ̀ yóò bá wúlò rárá, ó yẹ kí á rí àwòrán ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ láwùjọ
nínú rẹ̀. Àwọn tí ó ń kọ
ìtàn àròsọ wa kò ṣe èyí nígbà tí ọ̀rọ̀ kan àwọn Ọ̀mọ̀wé ẹgbẹ́ wọn. Wọn kò
bá ayé yí. Bí nǹkan ṣe
ń rí ni ọdún
mélòó kan sẹ́yìn ni wọ́n sì ń gbé hàn wá. Lóòótọ́, àwọn oníṣòwò, olóṣèlú àti àwọn
ọ̀gá ṣọ́jà ló gbayì láwùjọ wa ṣùgbọ́n àìkọ ìtàn àròsọ jáde àwọn wọ̀nyí kò
jẹ́ kí wọ́n gbé ọ̀rọ̀ ara wọn ga kí wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀ fi ọwọ́ ara wọn tún ìwà
ara wọn ṣe bíi ti àwọn Ọ̀mọ̀wé. Láìsì kọ ìtàn àròsọ tí a sọ yìí fúnra
wọn nípa ara wọn, n kò rò pé àwọn òǹkọ ìtàn àròsọ tí a ní báyìí yoò gba ọ̀rọ̀ wọn wí
gẹ́gẹ́ bí Smythe and Smythe (1967: 81)27 ṣe sọ wí pé
the educated Nigerians are usually aloof from the masses
Ìyẹn ni pé ń ṣe ni àwọn
Ọ̀mọ̀wé ọmọ Nàìjíríà máa ń ta kété sí ọ̀rọ̀ tí ó bá kan gbogbo ènìyàn. Èyí gan-an ni àwa ro pé
ó bá àwọn tí ó ń kọ
ìtàn àròsọ Yorùbá mu. Lójú tiwa, ọ̀rọ̀ ara won jẹ wọ́n lógún ju àwọn míràn
lọ.
Ìtọ́ka
1.
Ọba O. O. Oyesọsin Keji (1977: 3),
“Ipa àti Ipò tí Àwọn Ọba Kó ní Ilẹ̀ Yorùbá: Láyé Àtijọ́ àti Lóde Òní”, Yorùbá
Gbòde, Vol., 3, No. 4.
2.
Benedict M. Ibitokun (n.d.: 1 1),
“Revolt in Nigerian Novel: Kole Ọmọtọṣọ’s The Edifice, Sacrifice and
The Scales”. A
Seminar paper delivered at the
Department of African Languages and Literatures, Ilé-Ifẹ̀, Nigeria.
3.
Karin Barber (1979: 22), “Sociology of Yorùbá
Written Literature: Fágùnwà and Okèdíji”, A Seminar Paper Presented at the
Department of African Languages and Literatures, Ọbafẹ́mi Awólọ́wọ̀
Universiyt, Ilé-Ifẹ̀,
Nigeria.
4.
Tony Bennett (1979: 115), New
Accents: Formalism and Marxism, Methuen and Co. Ltd., London.
5.
O.B. Yai (1977: 4), “Ideas for a Political Reading of
Fagunwa”, A Conference Paper Presented at Orisha
Tradition held at the Unviersity of Ifẹ̀, Ilé-Ifẹ̀, Nigeria.
6.
Karin Barber (1979: 4), Op. cit.
7.
Ibid., pg. 22.
8.
Ibid., pg. 5
9.
Op. cit.
10. Op. cit.
11. Akínwùmí
Ìṣọ̀lá (n.d.: 27), “Images of the Ọba in Yorùbá Novels”, a Seminar Paper Presented at the
Department of African Languages and Literatures, University of Ife, Ilé-Ifẹ̀, Nigeria.
12. Op. cit
13. Peter
C.W. Gutkind (1975: 22), The View from Below: Political Consciousness of the
Urban Poor in Ibadan, Centre for Developing Area Studies, McGill
Univeristy.
14. Akínwùmí
Ìṣọ̀lá (1976: 395), “The Detective Novel in Yorùbá”, Department of African
Languages and Literatures Seminar Series, No. 1, 1976-77, Part II.
15. Karin
Barber (1979: 39), “Sociology of Yorùbá Written Literature: Fagunwa and
Okediji”, An unpublished Seminar Paper delivered
at Department of African
Languages and Literatures, University of Ife, Nigeria on the 9th
April, 1979.
16. Op. cit.
17. Robert
Tressel (1965), The Ragged Trouserred Philanthropists, with an
introduction by Allan Sillitoe, Panther Paperback, Lawrence and Wishart Ltd.,
London.
18. Peter
Nazareth (1967: 35), “A Committed Novel”, Transition, No. 29, Vol, 6
(iv), Feb./March 1967.
19. P.
Mercier (1966: 379), in P.C. Lloyed (ed.), The New Elites of Tropical
Africa, OUP, London.
20. Ọmọlara
Ogundipe-Lesilie (1981: 3), “A Marxist Reading of The Interpreters”, A
Seminar Paper Presented
at the Department of Literature in English and Department of Philosophy Joint
Seminar, University of Ibadan,
Nigeria, 25th March, 1981.
21. O.B. Yai
(1977: 10), Op. cit.
22. Ibid.
23. Op. cit.
24. Op. cit.
25. George
Lamming (1973: 61), In The Castle of my Skin, quoted from S. Wayak “V.S.
Naipaul and the West Indian Situation” Busara, Vol. 5, No. 1, 1973.
26. Kọ́lá
Ògúngbẹ̀san (1971: 61), “Literature and Society in West Africa” African
Quarterly, xi, 3.
27. Quoted
from F.O. Okediji and Opeyemi Ọla (1967: 81) “The Formation of New Elites in Tropical
Africa: A Review Article”, ODU,
vol. 4, No. 1.
28. Ayọ̀
Bamgboṣe (1974: 61). The Novels of D.O. Fágúnwà, Ethiope Publishing
Corporation, Benin City.
29. O.R.
Dathorne (1965: 63), “The African Novel – Document to Experiment”, Bulleting
of the Assocaition for African Literature in English, No. 3, November,
1965.
30. Ibid.
31. Movement
for Progressive Nigerians (1978: 23), “Nigerian Women and the Revolution of the
Nigerian People” Positive Review, No. 1, 1978.
32. Walter
Norman May (1965: 44), Gem of Thought: Wisdom and Inspiration, Gift
Edition Books Incorporation, Chicago.
33. Rev.
Samuel Johnson (1921: 201), The History of the Yorubas, (ed.) O. Johnson,
C.M.S. Bookshop, Lagos.
34. Walter
Benjamin (1977: 34), ‘Understanding Brecht’ New Left Books, London.
35. Op. cit
36. Hilary
Seymour (1983: 49), “Textual Silence: An Exploration of Patriarchy in Things
Fall Apart and God’s Bits of Wood. A Seminar Paper Presented at the
Department of Literature in English, University of Ife, Nigeria on the 5th of
May, 1983.
37. Ibid.
38. Ibid.,
pg. 20
39. Ibid.
40. Walter
Norman May (1965: 26), Op. cit.
41. Ibid.
42. Quoted
from Hilary Seymour (1983: 21), Op. cit.
43. Kamene
Okonjo (1976: 46), “Igbo Women and Community Politics”, in Women in Africa (eds.)
N.J. Hafkin and E.G. Bay. Stanford: Stanford University Press.
44. R.
George Horner (1971: 3), “Folklore as a Psychological Projective System”, The
Conch, Vol. 3, No. 1.
45. Op. cit.
46. Op. cit.
Àkọ́jo Orúkọ Ìwé
Ìwé Ìtàn
Àròsọ
Adeoye, C.L. (1966), Ẹ̀dá Ọmọ Oòduà, Onílé Owó
Press, Ìbàdàn (later by OUP, Ibadan, 1971).
Akinlade, K. (1971), Ta Ló Pa Ọmọ Ọba?,
Macmillan, Lagos.
Akinlade, K. (1971), Ọwọ́ Tẹ Amòòkùnṣìkà,
Macmillan, Lagos.
Akinlade, K. (1973), Aṣenibánidárò, Macmillan,
Lagos.
Akinlade, K. (1973), Ta Lolè Ajọ́mọgbé?, Macmillan, Lagos.
Akinlade, (1974), Alosi Ọlọ́gọ, Longman, Lagos.
Akinlade, (1976), Owó Ẹ̀jẹ̀, Oníbọn-òjé, Ìbàdàn.
Àkọ́jo Orúkọ Ìwé
Ìwé Ìtàn
Àròsọ
Adeoye, C.L. (1966), Ẹ̀dá Ọmọ Oòduà, Onílé Owó
Press, Ìbàdàn (later by OUP, Ibadan, 1971).
Akinlade, K. (1971), Ta Ló Pa Ọmọ Ọba?,
Macmillan, Lagos.
Akinlade, K. (1971), Ọwọ́ Tẹ Amòòkùnṣìkà,
Macmillan, Lagos.
Akinlade, K. (1973), Aṣenibánidárò, Macmillan,
Lagos.
Akinlade, K. (1973), Ta Lolè Ajọ́mọgbé?, Macmillan, Lagos.
Akinlade, (1974), Alosi Ọlọ́gọ, Longman, Lagos.
Akinlade, (1976), Owó Ẹ̀jẹ̀, Oníbọn-òjé, Ìbàdàn.
Akinlade, (1976), Àgbákò Nílé Tẹ́tẹ́, Evans,
Lagos.
Akintan, E.A. (1931), Ìgbẹ̀hìn Á Dùn, The Anchor.
Awoniyi, T.A. (1973). Ayékòótọ́, Oníbọnòjé,
Ìbàdàn.
Delanọ, I.O. (1955). Aiye Daiye Oyinbo, Thomas
Nelson and Sons, London.
Delanọ, I.O. (1963), Lọ́jọ́ Ọjọ́ Un, Thomas
Nelson and Sons, London.
Fadeṣere, P.I. (1978), Ajítòní, OUP, Ìbàdàn.
Fagunwa, D.O. (1938), Ògbójú Ọdẹ Nínú Igbó
Irúnmọlẹ̀, C.M.S. Nigeria Bookshops, Lagos (Later, by Thomas Nelson and
Sons, London 1950).
Fagunwa, (1949), Igbó Olódùmarè, Thomas Nelson and
Sons, London.
Fagunwa, (1949), Ìrèké Oníbùdó, Thomas Nelson and
Sons, London.
Fagunwa, (1594), Ìrìnkèrìndò Nínú Igbó Elégbèje,
Thoams Nelson and Sons, London.
Fagunwa, (1961), Àdììtú Olódùmarè, Thomas Nelson
and Sons, London.
Faleti, A. (1969), Ọmọ Olókùn Ẹṣin, U.LP.,
Port Harcourt.
Fatanmi, D.A. (1967), Kórímálẹ Nínú Igbó Àdìmúlà,
Thomas Nelson and Sons, London.
Ilara, Tunde (1977), Ẹ̀san Á Ké, Ladson
International, Ilé-Ifẹ̀.
Ìṣọ̀lá, A. (1974), Ó Le Kú, OUP, Ìbàdàn.
Ìṣọ̀lá, A. (1974), Ìgbà Èwe, UPL, Ìbàdàn.
Ìṣọ̀lá, A. (1974), Ogún Ọmọdé, UPL, Ìbàdàn.
Jẹbọda, Fẹ́mi (1964), Olówólaiyemọ, Longman,
Lagos.
Ladele, T.A. (1971). Jẹ Ń Lògbà Tèmi, Macmillan,
Lagos.
Ladele, T.A. (1978), Ìgbì Ayé Ń Yí, Longman,
Lagos.
Ogundele, J.O., (1956), Èjigbẹ̀dẹ́ Lọ́nà Ìsánlú Ọ̀run,
Longman, Lagos.
Ogundele, (1956), Ibú Olókun, University of London
Press, London.
Ogunniran, L. (1972), Eégún Aláré, Macmillan,
Lagos.
Okediji, O. (1969). Àjà Ló Lẹrù, Longman, Lagos.
Okediji, O. (1971), Àgbàlagbà Akàn, Longman,
Lagos.
Ọlabimtan, A. (1969), Kékeré Ẹkùn, Macmillan,
Lagos.
Ọlabimtan, A. (1973), Àyànmọ́, Macmillan, Lagos.
Ọlabimtan, A. (1978), Baba Rere, Macmillan,
Lagos.
Owólabí, O. (1974), Orí Adé Kì í Sunta, Macmillan,
Lagos.
Oyedele, A. (1947), Aiye Ree, Gaskiya Corporation,
Zaria.
Oyedele, A. (1970), Ìwọ Ni, Macmillan, Lagos.
Oyedele, A. (1970), Kini Mo Ṣe? Macmillan, Lagos.
Ọdunjọ, J.F. (1964), Kúyẹ̀, AUP, Lagos.
Ọdunjọ, JLF. (1964), Ọmọ Òkú Ọ̀run, AUP,
Lagos.
Ọdunjọ J.F. àti Ọladipupọ, A.B. (1967), Kádàrá àti
Ẹ̀gbọ́n Rẹ̀, Oníbọnòjé, Ìbàdàn.
Ọmọyajowo, J.A. (1957), Ìtàn Ọdẹ́níyà, Adégbàmí
and Sons Press, Agbor.
Ọmọyajowo, J.A. (1961), Báyọ̀ Ajọ́mọgbé,
Longman, Lagos.
Ṣobande, O.A. (1959), Rìgímọ̀ Obìnrin Kò Ṣe é Tú, Tìkà
Toore Press, Lagos.
Yemitan, O. (1972), Gbọ́baníyì, O.U.P., Ìbàdàn.
Yemitan, O. (1980), Orúkọ Ló Yàtọ̀, UPL., Ìbàdàn.
Ìwé Àpilẹ̀kọ àti Ìwé Àtẹ̀jáde
Bamgboṣe, Ayọ̀ (1974), The Novels of D.O. Fagunwa, Ethiope
Publishing Corporation, Benin City, Nigeria.
Barber, Karin (1979), “Sociology of Written Literature:
Fagunwa and Okediji”, A Semianr Paper delviered at the Department of African
Languages and Literatures, University of Ife, Nigeria on the March 9th, 1979.
Benjamin, Walter (1977), “Understanding Brecht”, New
Left Books, London.
Bennet Tpny (1977), New Accents, Formalism and
Marxism, Methuen and Co. Ltd., London.
Boa, E. and J.H. Reaid (1972), Critical Strategies, Edward
Arnold Publishers Ltd., London.
Cabral, Amilcar (1969). Revolution in Guinea, Stage
One, London.
Coker, Cheyney Syl (1973), Concerto for Exile,
Heinemann, London.
Dada, P.O. (1980), “Marxist Criticism and African
Literature”, Ganga, Vol. 2, No. 4.
Dathorne, O.R. (1965), “The African Novel – Document to
Experiment”, Bulletin of the Association for African Literature in English,
No. 3, November, 1965.
Eagleton, Terry (1977), Marxims and Literary Criticism,
Methuen and Co. Ltd., London.
Echeruo, Michael J.C. (1967), “Robinson Crusoe, Purchase
his Pilgrim and his Novel”, English Studies in Africa, Vol. 10, No. 2.
Goldman, Lucien (1975), “Dialectical Materialism and
Literary History”, Toward a Sociology of The Novel, London, Tavistock.
Gutkind, Peter C.W. (1975), The View from Below:
Political Consciousness of the Urban Poor in Ibadan, Centre for
Devleoping-Area, McGill University.
Horner, George R. (1971), “Folklore as a Psycholgocial
Projective System”, The Conch, Vol. 3, No. 1.
Ibitokun, Benedict M. (n.d.), “Revolt in Nigerian Novel:
Kole Ọmọtọṣọ’s The Edifice, Sacrifice and The Scales. A Seminar Paper Delviered at the
Department of African Languages and Literarues, University of Ife, Ile-Ife, Nigeria.
Irele, Abiola (1977), “Study African Literature”. Nigerian
Journal of Humanities, Vol. 1,. No. 1.
Ìṣọ̀lá, A. (1979), “Presenting Revolution in Ọmọ
Olókùn Ẹsin”, A Seminar Paper Presented at the Department of African Languages and
Literatures, Univeristy of Ifẹ, Ilé-Ifẹ̀, Nigeria on 26th February, 1979.
Jackson, I.F. (1956), Advance in Africa, OUP,
London.
Johnson, Rev. Samuel (1921), The History of the
Yorubas, (ed.) Johnson, O., CMS Bookshop, Lagos.
Lowenthal, Leo (1957), Literature and the Image of Man,
Boston, Mass.
Lukacs, George (1963), The Meaning of Contemporary
Realism, Merlin Press, London.
My, Walter Norman (1965), Gem of Thought: Wisdom and
Inspiration, Gift Edition Books Incorporation, Chicago.
Nazareth, Peter (1967), “A Committed Novel”, Transition,
No. 29, Vol. 26(iv), Feb./March 1967.
Nkrumah, Kwame (1970), Class Struggle in Africa,
International Publishers, New York.
Ogundipe-Leslie, Ọmọlara (1981), “A Marxist Reading of The Interpreters”, A Seminar Paper Presented at the
Department of Literature-in-English and Department of Philosophy Joint Seminar,
Unviersity of Ibadan,
Nigeria on March 25th, 1981.
Ogungbẹsan, Kọ́lá (1971), “Literature and Society in West Africa”, African
Quarterly, xi, 3.
Okediji, F.O. and Ọla Ọpẹyẹmi (1967), “The Formation
of New Elites in Tropical Africa: A Review Article”, ODU, Vol 4, No. 1.
Okonjo, Kamene (1976, “Igbo Women and Community Poltiics”,
in Women in Africa (eds) Hafkin, N.J. and E.G. Bay, Stanford University
Press, Stanford.
Oyesọsin, Ọba O.O. (1977), “Ipa àti Ipò tí àwọn Ọba Kó ní Ilẹ̀ Yorùbá: Láyé
Àtijọ́ àti lóde Òní”, Yorùbá
Gbòde, Vol. 3, No. 4.
Seymour, Hlary (1983), Textual Silence: An Exploration of
Patriarchy in Things Fall Apart and God’s Bits of Wood”, A
Seminar Paper Presented
at the Deparment of Literature-in-English, Univeristy of Ife, Nigeria on the 5th of
May, 1983.
Shuking, L. (1944), The Sociology of Literary Taste,
London.
Tressel, Robert (1965), The Ragged Trousered
Philanthropists, with an introduction by Silitoe, Allan, Panther Paperback,
Lawrence and Wishart Ltd., London.
Yai, O.B. (1977), “Ideas for a poltiical Reading of
Fagunwa”, A Conference Paper Presented at the
Orisha traditon, held at the University of Ife, Ile-Ife, Nigeria.
Zhdnov, Vladimir (1956), “Some Recent Soviet Studies in
Literature”, Soviet Literature, No. 8, Moscow.
No comments:
Post a Comment