Saturday, 27 August 2016

IPÒ ÀLỌ́ NÍNÚ AKITIYAN ÌTANIJÍ


 
Abíọ́dún Abọ́dúndé

1.      Ọ̀rọ̀ Àkọ́sọ[1]

          Ariwo tí a ń gbọ́ káàkiri gbogbo ìpínlẹ̀ tó para pọ̀ di orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lónìí ni ìpè fún ìtanijí gbogbo olùgbé àṣùwàdà ènìyàn yìí sí ojúṣe ẹni kọ̀ọ̀kan fún ìdàgbàsókè àti ìlọsíwájú orílẹ̀-èdè náà lápapọ̀. Láti lè jẹ́ ìpè náà bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ, ó yẹ kí kálukú wa kọ́kọ́ ṣe àyèwò ara rẹ̀ bí òun gan-an alára bá mọ ojúṣe rẹ̀ sí orílẹ̀-èdè rẹ̀. Ó dìgbà tí a bá lè yangàn fúnra wa pé àwa gan-an lápapò àti ní ẹni kọ̀ọ̀kan mọ ojúṣe wa sí orílẹ̀-èdè wa ká tó lè fọwọ́ sọ̀yà pé a tó ìpè ìjọba í jẹ́, fún ìtanijí gbogbo ènìyàn yòókù sí ojúṣe wọn fún ìdàgbàsókè àti ìlọsíwájú orílẹ̀-èdè wa.

          Ẹni tí kò mọ àṣà fún ìbágbépọ̀ ìrọ̀rùn pẹ̀lú àwọn ènìyàn àyíká rẹ̀, kò lè yangàn pé òun mọ ojúṣe òun fún ìdàgbàsókè àti ìlọsíwájú àwùjọ gan-an tó ń gbé, débi tí yóò mọ ojúṣe rẹ̀ sí orílẹ̀-èdè rẹ̀ lápapọ̀ (Awóníyì, 1975:363). Nítorí ìmọrírì òdodo ọ̀rọ̀ pé “ilé la ti í kẹ́sọ̀ọ́ rode”, ló fi yẹ pé kí gbogbo ọmọ Yorùbá kọ́kọ́ ṣe àgbéyẹ̀wò ojúṣe wọn bó bá tọ̀nà, kí wọn tó lè kópa tó gúnmọ láwùjọ gbogbo olùgbé orílẹ̀-èdè yìí nínú jíjẹ́ ìpè ìjọba.

          Nírorí pé a nígbàgbọ́ pé ó ṣeé ṣe pé kí ọ̀pọ̀ nínú àwọn àgbà Yorùbá tí dáńgájíá nínú ìmọ̀ àti ìlò àṣà ọmọlúwàbí láwùjọ la ṣe dojú iṣẹ́ yìí kọ àwọn ògo wẹẹrẹ ní pàtàkì jù lọ, tó ṣe ṣe pé kí wọn má mọwọ́ ọ̀tún dá yatọ̀ sí tòṣì nípa ọ̀rọ̀ tó jẹ mọ́ ìwà ọmọlúwàbí tí í gbé orílẹ̀-èdè dé èbúté rere.

2.      Oríkì Àṣà[2]

          Àṣà ènìyàn kan pàtó ni ìṣesí tàbí ìhùwàsí tí a mọ̀ mọ olúwarẹ̀, tó yà á sọ́tò sí ẹ̀dá ènìyàn mìíràn. Yorùbá a máa lo ọ̀rọ̀ ìṣe ‘dá’ fún ìṣesí tàbí ìhùwàsí tí a kà kún àṣà. Wọn a ní ènìyàn ‘dá’ àṣà tó rí ṣà fúnra rẹ̀ ní àyíká rẹ̀. Ènìyàn sì lè ‘kọ́’ àṣà lọ́dọ̀ ẹni tó rìn pàdé tàbí tó bá gbé pò láyìíká, bẹ́ẹ̀ sì ni ènìyàn lè jogún àṣà lọ́dọ̀ àwọn òbí rẹ̀. Wọn a ní ènìyàn káṣà (kọ́ àṣà)[3] aláṣà.,

          Bí àṣà rere ti wà náà ni àṣà burúkú wà. Ṣé tibitire la dálé ayé. Gbogbo ìṣesí àti ìhùwàsí tó yẹ ọmọlúwàbí ènìyàn tó sì lè ṣeé bá ẹ̀dá ènìyàn tí a ń bá gbé pọ̀ láwùjọ lára mu débi pé ó lè ṣe àwa àtàwọn láǹfààní ni a kà kún àṣà rere (Awóníyì, 1975:357).  Nídà kejì ẹ̀wẹ̀, ìṣesí àti ìhùwàsí yòówù tí kò lè ṣe ẹ̀dá ènìyàn, yálà, ẹni tó ṣèṣe tàbí tí ó hùwà náà fúnra rẹ̀, àwọn alájọgbó tàbí alábàágbé rè láwùjọ láǹfààní, tó tilẹ̀ lè pa òun fúnra rẹ̀ tàbí àwọn ẹlòmíràn lára tàbí tí ó lè ṣe wọ́n níjàmbá ni a kà kún àṣà tàbí ìwà burúkú (Abímbọ́lá, 1975:389). Fún àpẹẹrẹ, àwọn ìhùwàsí bí olè jíjà, ìmẹ́lẹ́ tàbí ọ̀lẹ síṣe, ìpànìyàn, ìdigunjalè, ìṣàgbèrè, ahun síṣe, òfófó síṣe, ìdìtẹ̀, ìjáfara, ìgbéraga àti àwọn ìhùwàsí búburú mìíràn tó lòdì sí ìfẹ́ àwùjọ ènìyàn ni a kà kún àṣà burúkù.

          Nígbà tí ìṣesí tàbí ìhùwàsí kàn bá di bárakú fún ẹ̀dá ènìyàn kan ni a máa ń kà á kún àṣà rẹ̀, ì báà ṣe àṣà rere tàbí àṣà burúkù. Bí Yorùbá bá ṣàkíyèsí pé ẹ̀dá ènìyàn kan ní àṣà rere kan tó ń ṣe é ní àǹfààní tó hànde, wọn a máa là kaka láti kọ́ irú àṣà bẹ́ẹ̀ tí wọn kò bá tíì ní in tẹ́lẹ̀. Nídà kejì ẹ̀wẹ̀, tí Yorùbá bá mọ ènìyàn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ mọ́ àṣà burúkú kan, wọn a máa sára fúnrú ẹni bẹ́ẹ̀ kó má baà kó àṣà burúkú ọwọ́ rẹ̀ ràn wọ́n. Wọn a tilẹ̀ máa ki ẹni wọn nílọ̀ pé kó má ṣe bá aláṣà burúkú náà rìn kó má baà kó àṣà burúkú tí a ti mọ̀ ọ́n mọ́ ran onítọ̀hún.

 

3.      Àlọ́ àti Àṣà

3.1    Ìfáárà

          Ipò pàtàkì ni Yorùbá to àlọ́ sí lágbo ńlá lítíréṣọ́ nípa kíkọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ àṣà. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú ‘lílò’ tí Bascom dábàá gẹ́gẹ́ bíi tíọ́rì tó tọ̀nà jù lọ láti máa fi ṣe àtúpalẹ̀ lítíréṣọ̀ àti àwọn ọmọ ìyá rẹ̀ gbogbo, bí ìtàn ìwáṣẹ̀ àti fókìlọọ̀ (Dorson, 1972:21). Ẹ̀dá inú àlọ́ ni apàlọ́ hun àṣà tó fẹ́ fi kọ́ àwùjọ̀ lọ́gbọ́n mọ́ lára. Lára ohun tí apàlọ́ ń kíyè sí kó tó gbé ìṣẹ́ fún ẹ̀dá yòówù ó jẹ́ nínú àlọ́ ni bí àbùdá, ìrísí, ìṣesí àti ìhùwàsí tí apàlọ́ ti mọ̀ mọ irú ẹ̀dá bẹ́ẹ̀ ṣe lẹ̀ ràn án lọ́wọ́ láti jẹ́ irú iṣẹ́ tí a fẹ́ gbé fún un náà (Finnegan, 1967:344-346). Fún àpẹẹrẹ, iṣẹ́ tí í fi èrè ìwà ọ̀dàlẹ̀, tẹ̀mbẹ̀lẹ̀kun, ọgbọ́n àrékérekè, ọgbọ́n ẹ̀wẹ́, ọgbọ́n ìjàǹbá hàn ni apàlọ sáábà ń rán alábahun Ìjàpá nínú àlọ́ (Babalọlá, 1973).

          Nígbà tí àpàlọ́ bá fẹ́ rán ahun nírú iṣẹ́ báwọ̀nyí, ó sáábà ń fi ẹ̀dá mìíràn tí ìhùwàsí àti àbùdá rẹ̀ lòdì sí ti alábahun ta ko Ìjàpá. Dípò pé kí apálọ́ (olùsẹ̀dá àlọ́) jẹ́ kí ẹ̀kọ́ tó fẹ́ fi ìtàn inú àlọ́ náà kọ́ àwùjọ hàn ní kíákíá, ó máa ń fún àwọn ẹ̀dá inú àlọ́ náà láyè láti tayò àmúlò àṣà tàbí ọgbọ́n rere àti búburú, bó tílẹ̀ jẹ́ pé àṣà tàbí ọgbọ́n tí apàlọ́ gbàgbọ́ pé ó wúlò, tó sì fẹ́ fi kọ́ àwùjọ ni yóò pàpà jẹ́ kó borí ọgbọ́n tí àwùjọ lòdì sí, ṣùgbọ́n tó ti fún ẹ̀dá inú àlọ́ náà lò ní àlòtẹ́rùn. Níbi tí àwọn ẹ̀dà inú àlọ́ ti ń tàkòtó àmúlò ọgbọ́n ni ẹ̀kọ́ inú àlọ́ ti í hàn sí olóye ènìyàn kí apàlọ́ wá tó fa ọgbọ́n yọ ní ìkádìí àlọ́, pàápàá fún ọmọdé.

          Fún àpẹẹrẹ, nínú àlọ́ ‘Ìjàpá Rí Ilẹ̀ tí ó lójú’ (Babalọlá, 1973b:70) ni apàlọ́ ti fi ìwà sùúrù, ìwà pẹ̀lẹ́ àti làákàyè ẹyẹlé ta ko ìwà ojúkòkòrò, ànìkànjopọ́n àti àrékérekè alábahun Ìjàpá. Nígbà tí apàlọ́ náà ń hun ìtàn inú àlọ́ nàá pọ̀ mọ́ àwọn olú ẹ̀dá tó lò, ìjàpá, ẹyẹlé, àna ẹyẹlé, abbl., ó mú kí àwọn olú ẹ̀dá ìtàn méjèèjì, ìjàpá àti ẹyẹlé, máa yí ara wọn sébè àti sí poro nípa àmúlò ọgbọ́n. Bí alábahun ti ń fi ọgbọ́n ẹ̀wẹ́ tí a mọ̀ ọ́n mọ́ jẹ ẹyẹlé níyà, náà ni ẹyẹlé ń fi ìwà sùúrù àti làákàyè jàjàgbara. Nítorí ẹ̀kọ́ tí apàlọ́ fẹ́ fi kọ́ àwùjọ nínú àlọ́ náà, pé ‘àkọ́dá oró kò dà bí oró àdágbẹ̀yìn’, ó fi àyè gba alábahun Ìjàpá láti kọ́kọ́ fi ọgbọ́n àrékérekè jẹ ẹyẹlẹ́ níyà kí apàlọ́ ọ̀hún tó wá fún ẹyẹlé láyè láti fi hàn pé bẹbẹ ọgbọ́n kò pin sọ́dọ̀ ẹni kan ṣoṣo.

          Lára àwọn ìwà burúkù tí a ti mọ̀ mọ alábahun Ìjàpá, tí a sì fún un láyè láti hù tẹ́rùn nínú àlọ́ òkè yẹn ni ìwà àìsòótọ́, àìṣeégbẹ́kẹ̀lẹ́, àrékérekè, wọ̀bìà, ojúkòkòrò, ahun, àṣerínikójẹ, àjẹkì, ọ̀kánjúà, àgàbàgebè, òfófó, ìfèrúgbàbùkún àti ẹnu-àìmẹ́nu. Gbogbo ìhùwàsí wọ̀nyí àti irú wọn mìíràn ni àwùjọ Yorùbá lòdì sí. Lára àwọn ìwà tó bá àwùjọ lára mu tí apàlọ́ mú kí ẹyẹlé hù nínú àlọ́ náà ni ìwà ìfẹ́ tòótọ́, ìpamọ́ra, sùúrù, ìtẹ́lọ́rùn, ìwà tútù àti ọgbọ́n inú.

          Nínú àlọ́ ‘Ìjàpá jí iṣu Ìgbín àná rẹ̀’ (Babalọlá, 1973a:107) apàlọ́ hun onírúurú èrè àṣà tó jẹ mọ́ olè jíjà mọ́ Ìjàpá àti Ìgbín àna rẹ̀ lára. Ìjàpá jèrè ìtìjú nígbà tí Ìgbín àna rẹ̀ jèrè ìwà àṣejù. Nínú àlọ́ mìíràn, ‘Òjòlá ṣahun sí Ìjàpá’ (Babalọlá, 1973b:132).  ni apàlọ́ ti hun èrè àṣà ahun síṣe pọ̀ mọ́ Ìjàpá àti Òjòlá lára  ṣùgbọ́n Ìjàpá ṣe àmúlò ọgbọ́n ẹ̀wẹ́ láti jẹ Òjòlá lójèé; èyí tó fa òwe ‘ènìyàn ní í kọ́ni pé ká gùn, ènìyàn ní sì í kọ́ni pé ká kúrú.’ Nínú àlọ́ mìíràn ni apàlọ́ ti hun ẹ̀kọ́ àṣà àmúlò ọgbọ́n pọ̀ mọ́ Ìjàpá (kòtòǹkan ẹranko) àti erinmi (tó tóbi jù lọ láwùjọ ẹran inú omi). Nínú àlọ́ yìí, ‘Ìjàpá, Erin Òkè àti Erinmi’ (Babalọlá, 1973a:56), ni Ìjàpá ti fi ọgbọ́n ẹ̀wẹ́ jẹ àwọn ‘atóbanti má lọ́gbọ́n nínú’ ẹranko wọ̀nyí lójèé, èyí tó bí àkànlò èdè ‘ọgbọ́n ju agbára’. Yàtọ̀ sí àwọn àpẹẹrẹ àlọ́ òkè wọ̀nyẹn, onírúurú àlọ́ mìíràn tó fi ìbáṣepọ̀ ènìyàn sí ènìyàn àti ènìyàn sí ẹranko hàn lò wà, tó sì wúlò fún ìtanijí sí àṣà tó wúlò fún ìbágbépọ̀ ènìyàn ní àwùjọ. Fún àpẹẹrẹ, nínú àlọ́ ‘Ọmọ́yọ àti Erè: (Abọ́dúndé: tó ń bọ̀ lọ́nà) ni apàlọ́ ti hua ọ̀kan-ò-jọ̀kan àpẹẹrẹ àṣà àwùjọ pọ̀ mọ́ra wọn sí. Nígbà tí alóyinlétè apàlọ́ yóò bá fi kádìí àlọ́ náà ni onírúurú ẹ̀kọ́ yóò ti hànde.

          Nínú àṣà àsùwàdà ènìyàn tó para pọ̀ sínú àlọ́ náà la ti rí

3.2    Àwọn Ohun tí a máa ń Rí nínú Àṣà Asùwàdà Ènìyàn

3.2. 1.         Àṣà Ẹbí Síṣe

          Ìpìlẹ̀ ẹbí nílẹ̀ Yorùbá ni ọkọ (baba Ọmọ́yọ), ìyàwó (ìyá Ọmọ́yọ) ọmọ (Ọmọ́yọ). Ọmọ́yọ, ọ̀dọ́mọbìnrin awẹ́lẹ́wà tó ń wá ọkọ ni àpẹẹrẹ ète ìfẹ̀lójú mọ̀lẹ́bí. Nígbà tí Ọmọ́yọ bá lọ́kọ, òun àti ọkọ tirẹ̀ ni yóò bẹ̀rẹ̀ ẹbí tuntun, nípa bẹ́ẹ̀, igi ẹbí tí baba Ọmọ́yọ gbìn bẹ̀rẹ̀ sí í pẹka nìyẹn.

 

3.2.2.          Ìgbàgbọ́ Yorùbá

          Èyí ni apàlọ́ ń fìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbáṣepọ̀ tó wáyé láàrin Ọmọyọ (ẹ̀dá ènìyàn) àti ẹbọra (erò tó gbáwọ̀ ẹ̀dá ènìyàn wọ̀) pẹ̀lú ète àtinájà aráyè. Àṣífẹ́ wáyé láàrin Ọmọ́yọ (ènìyàn) àti erè (àdàmọ̀dènìyàn). Agbára ẹbọra ta ti ènìyàn yọ nípa àyípadà sí ẹ̀dá ènìyàn tó máa ń rọ̀ wọ́n lọ́rùn láti ṣe gẹ́gẹ́ ìgbàgbọ́ ènìyàn.

 

3.2.3.          Àfìhàn Àṣà Iṣẹ́ Ọdẹ Ṣíṣe

          Ọdẹ ni olùgbàlà Ọmọ́yọ nínú àlọ́ yìí. Agbára tí ẹlẹ́dàá fún ẹ̀dá ènìyàn lórí ẹranko ló jẹ́ kí ọdẹ kápá erè nígbà tó ń ṣèṣe ẹranko lọ́wọ́. Èyí tún fi pàtàkì iṣẹ́ ọdẹ hàn; èyí tí í ṣe ààbò ìlú àti olùgbé rẹ̀.

 

3.2.4.          Àṣà Ọjà Níná

          Jákèjádò ilẹ̀ Yorùbá la ti í nájà òòjọ́ (ojoojúmọ́), ọrọọrún, isiisán, ìtàdógún, abbl. Ìgbàgbọ́ Yorùbá sí ni pé àtènìyàn àtẹbọra pẹ̀lú ẹ̀mí àìrí mìíràn gbogbo ní í ṣe àkọlùkọgbà nínú ọjà lásìkò tí ọjà níná bá ń lọ lọ́wọ́.

3.2.5.          Èrè Ìwà Ìgbéraga

          Ọmọ́yọ fi ìwà ìgbéraga lòdì sí àṣà rere tí í ṣe ìgbọràn. Tó bá jẹ́ pé Ọmọyọ gbọ́ràn sí àwọn òbí rẹ̀ lẹ́nu nípa pé kó gbà láti fẹ́ ọkọ láàrin ènìyàn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, kì bá tí fojú kòkòrò kàgbákò ẹbọra tó ṣì fẹ́ ẹ lọ́kọ. Ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ Ọmọ́yọ ló ń dúró de ọmọdé tí kò bọ̀wọ̀ fún òbí rẹ̀ nípa gbígbọ́ràn sí wọn lẹ́nu.

 

3.2.6.          Ohun Èlò Iṣẹ́ Ọdẹ

          Ọ̀bẹ aṣóró tí ọdẹ fi pa ẹbọra erè jẹ́ ọ̀kan lára ohun èlò iṣẹ́ ọdẹ.

 

3..2.7.         Orin Kíkọ

          Ipò iyọ̀ amọ́bẹ̀dùn ni apàlọ́ to orin kíkọ́ sí nínú àlọ́ àpagbè. Orin kíkọ kì í jẹ́ kí òǹwòran àlọ́ sùn lọ títí tí wọn yóò fi rí ẹ̀kọ́ fà yọ nínú ìtàn àlọ́. Orin àlọ́, lọ́pọ̀ ìgb, a máa jẹ́ ìsọníṣókí ìtàn inú àlọ́. Àtúnkọtúnkọ rẹ̀ sì máa ń gbin ẹ̀kọ́/kókó inú àlọ́ sọ́kàn olùgbọ́ àti èrò ìwòran.

 

3.2.8.          Ọnà Àlọ́ Àpagbè

          Ìtàkúrọ̀sọ tó ń wáyé láàrin apàlọ́ àti elègbè àlọ́ ní ìbẹ̀rẹ̀ àlọ́ òkè yìí wà ní ìbámu pẹ̀lú àṣà. Ọ̀nà àtimáaṣe àkójọ àwọn elègbè orin àlọ́ ni ó jẹ́ ìdí pàtàkì kan tó fi í wáyé. Nígbà mìíràn, apàlọ́ a máa fi àlọ́ àpamọ̀ bíi mélòó kan, àrọ̀ jíjá tàbí ìmọ́ bíbú kún bátànì ìtàkúrọ̀sọ bẹ́ẹ̀.

 

3.2.9.          Ìkádìí Àló

          Ìdí àlọ́ mi rèé gbáńgbáláká

          Ìdí àlọ́ mi rèé gbàǹgbàlàkà …’

Kò ní ìtumọ̀ kan pàtó ju ète ìfọ̀rọ̀dárà, tó tún jẹ́ ìpèdè tó ya àlọ́ sọ́tọ̀ sí ẹ̀yà lítíréṣọ̀ mìíràn. Ọgbọ́n àtimú ìtàn dùn náà ni.

          Onírúurú ọnà èdè ni apàlọ́ máa ń mú lò láti hun ìtàn inú àlọ́ pọ̀, tó ń mú kí àlọ́ dùn kó sì lárinrin. Irú ọnà èdè bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ aṣàpèjúwe (àpèjúwe ẹwà ọmọkùnrin tí wọ Ọmọ́yọ lójú), àwítúnwí, àfiwé (dára bí egbin).

 

3..2.9.         Àló gẹ́gẹ́ bíi díńgí

          Nígbà mìíràn, Yorùbá a máa lo àlọ́ gẹ́gẹ́ bíi díńgí láti fi wo ohun tí wọn ì bá fẹ́ lọ́kàn wọn pé kó ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n bí ó tilè jẹ́ pé ìtàn, àwígbọ́ tàbí ìrírí kò fi hàn pé ó ṣẹlẹ̀ rí tàbí pé ó lè ṣẹlẹ́ ní ìgbésí ayé ènìyàn. Alábahun Ìjàpá jẹ́ ọ̀kan pàtàkì nínú èròjà àyíká tí àwọn apàlọ́ sáábà ń hun irúfẹ́ àlọ́ bẹ́ẹ̀ mọ́ lára. Ète ìkìlọ̀ ìwà ‘àlá  ọ̀sán’ tí í ṣokùnfà ìwà ojúkòkòrò, tó jẹ́ ìpìlẹ̀ ìwà bí ìdigunjalè la bá débi irú àlọ́ bẹ́ẹ̀. Fún àpẹẹrẹ,  àlọ́ ‘Ìjàpá àti àbọ̀n ẹyìn’ (Babalọlá, 1973a:29) lọ báyìí:

                  

Nígbà tí ìyàn mú ní ìlú Ìjàpá, Ìjàpá lọ ko àbọ̀n ẹyìn kan tó bọ́ sínú òkun. Ìjàpá kán lu omi òkun pẹ̀lú ìlàkàkà àtitọ̀pa àbọ̀n ẹyin náà délé olókun, ọba omi. Olókun ṣàánú Ìjàpá nípa pé ó fún un ní àràmọ̀ǹdà ìgbakọ kan tó lè pèsè gbogbo ohun tí ẹnu ń jẹ tí Ìjàpá bá ti lè sọ pé ‘Ìgbakọǹkọyán, ìgbakọǹkọkà, ìgbakọǹkọ gbogboǹkan fẹ́lẹ́fẹ̀lẹ’. Ìjàpà lo ìgbakọ yìí làti rọ̀yàn òun àti mọ̀lẹ́bí rẹ̀, kó tó fi ayọ̀ fọ́ ọ, tó sì pàdánu ìgbakọ̀ náà pẹ̀lú ìjìyà tó dógbin…

 

Apàlọ́ jẹ́ kí Ìjàpá pàdánù àràmọ̀ǹdà ìgbákọ pẹ̀lú ìjìyà tó dógbin láti kó ‘àlá ọ̀sán’ náà kúrò lọ́kàn olùgbọ́ tó lè máa rò lọ́kàn ara rẹ̀ pé irú ìṣẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ lè ṣẹlẹ̀ lójú ayé kó sì máa lépa rẹ̀ lọ́kàn ara rẹ̀.

Nígbà tí a rí àpẹẹrẹ àṣà Yorùbá tó pọ̀ tó tòkè yẹn fà yọ nínú àpẹẹrẹ àlọ́ tí a lò lókè yẹn, a kò ṣàìmọ̀ pé ẹni tó pe àlọ́ ní ibú àṣà Yorùbá kò jayò pa, pàápàá, bí a bá fojú inú wo ọ̀kẹ́-àìmọ̀ye àpẹẹrẹ àṣà tí a lè bá pàdé nínú ogunlọ́gọ̀ àlọ́ tó wà.

 

4.      Àgbálọgbábọ̀

          Yorùbá bọ̀, wọ́n ní ‘Ó rọrùn láti mú igi gùn látìsàlẹ̀ ju ká múgi gùn látòkè lọ̀’. Àìtìdí-múgi ẹ̀kọ́ àṣà gùn nípa ìdánilẹ́kọ̀ọ́ àwọn ògo wẹẹrẹ wa bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ láti ìbẹ̀rẹ̀-pẹ̀pẹ̀ ayé wọn ló fa ìpè àpàpàǹdodo fún ìtanijí tó gbòde kan báyìí.

          Ọ̀kan pàtàkì nínú èròjà àjogúnbá tí a ní ṣùgbọ́n tí a kò kọbi-ara sí lílò rẹ̀ ni àlọ́ jẹ́. Àlọ́ jẹ́ ọ̀nà pàtàkì tí àtìrandíran Yorùbá fi í kọ́mọ lẹ́kọ̀ọ́ àṣà látìgbà ìwáṣẹ̀. Àìkọbi-ara sí ìlò àlọ́ bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ ká ṣe kún ohun tó jẹ́ kí ìwà búburú gbogbo gbòde kan nílẹ̀ wa lónìí, tó sì fa ariwo ìtanjijí àwùjọ wa sí ojúṣe ẹni kọ̀ọ̀kàn tí à ń pa báyìí. Ṣùgbọ́n ó sì bà ni, kòì bàjẹ́. Kó má baà bàjẹ́ tán ló fi yẹ kí á tètè ṣán ṣòkòtò wa kó le, nípa àmúlò àlọ́ àti ẹ̀ka lítíréṣọ̀ wa yòókù tí àwọn baba-ńlá Yorùbá ti hun àṣà rere àti ọgbọ́n-àmúlò-ṣelé-ayé-ẹni mọ́ lára, fún kíkọ́ àwọn ògo wẹẹrẹ wa lẹ́kọ̀ọ́ ìwà rere. Èyí ló lè mú kí ìdàrúdàpọ̀ tó ń dún mọ̀huru-mọ̀huru mọ́ wa lórílẹ̀-èdè yìí lọ́wọ́lọ́wọ́ dáwọ́ dúró.

 

Ìwé Ìtọ́kasí

Abímbọ́lá, Wándé (1975), “Ìwàpẹ̀lẹ́: The Concept of Good Character in Ifá Literary Corpus.” in  Yorùbá Oral

Tradition: Poetry in Music, Dance and Drama, edited by  Wándé Abímbọ́lá, pp. 389-420. Ile-Ife, Nigeria:  Department of African Languages and Literatures, Obafemi Awolowo University..

Abọ́dúndé, Abíọ́dún (forthcoming), Àlọ́ Pípa Nílẹ̀ Yorùbá. Ìbàdàn: New Horn Press Ltd.

Awóníyì, T.A. (1975), “Ọmọlúwàbí: The Fundamental Basis of Yorùbá Traditional Education”. in Yorùbá Oral Treadition: Poetry in Music Dance and Drama, edited by Wándé Abímbọ́lá, pp. 358-388. Ile-Ife, Nigeria: Department of African Languages and Literatures, Obafemi Awolowo University.

Babalọlá, Adébóyè (1973), Àkójọpọ̀ Àlọ́ Ìjàpá (2 Vols.). Ìbàdàn: University Press Ltd.

Dorson, Richard, M. (1972), Folklore and Folklife: An Interoduction. Chicago: The University of Chicago Press.

Finnegan, Ruth (1967), Oral Literature in Africa. Clarendon: Oxford University Press.

 



[1] This work was published as Abodunde, Abiodun (1989), ‘Ipò Àlọ́ nínú Akitiyan Ìtanijí Àṣà Àwùjọ’, Seminar Series 2, edited by T.M. Ilesanmi, L.O. Adewole and B.A. Oyetade, pp. 108-121. Ile-Ife, Nigeria: Department of African Languages and Literatures, Obafemi Awolowo University.
[2] Nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé tí àwọn òǹkọ̀wé ti kọ tó sì wà lórí àtẹ ni wọ́n ti mẹ́nu ba ọ̀rọ̀ tó jẹ mọ́ àṣà, pàápàá, ìtumọ̀ tí a lè fún ọ̀rọ̀ náà ‘àṣà’.
[3] Bí kó + àṣà ṣe lè fún wa ní káṣà náà ni kó + àṣà ṣe lè fún wa ní kásà. Ohun tí a bá kọ lọ́dọ̀ ẹlòmíràn tó bá jẹ mọ́ àṣà, kíkọ́ náà la kọ́ ọ.

No comments:

Post a Comment